< Psalms 37 >
1 Ti Dafidi. Má ṣe ìkanra nítorí àwọn olùṣe búburú, kí ìwọ má sì ṣe ṣe ìlara nítorí àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀;
Do not be bothered/upset by what wicked [people do]. Do not desire to have the things that people who do wrong/evil have,
2 nítorí pé wọn yóò gbẹ bí i koríko, wọn yóò sì rẹ̀ dànù bí ewéko tútù.
because they will soon disappear, like grass withers [in the hot sun] and dries up. Just like some green plants [come up but] die [during the hot summer], evil people will soon die also.
3 Gbẹ́kẹ̀lé Olúwa, kí o sì máa ṣe rere; torí pé ìwọ yóò gbé ilẹ̀ náà, kí o sì gbádùn ààbò rẹ̀.
Trust in Yahweh, and do what is good; if you do that, you will live safely in the land [that he has given you], and you will live peacefully [MET].
4 Ṣe inú dídùn sí Olúwa; òun yóò sì fún ọ ní ìfẹ́ inú rẹ̀.
Be delighted with all that Yahweh [does for you]; if you do that, he will give you the things that you desire most.
5 Fi ọ̀nà rẹ lé Olúwa lọ́wọ́; gbẹ́kẹ̀lé pẹ̀lú, òun yóò sì ṣe é.
Commit to Yahweh all the things that you plan to do; trust in him, and he will do [whatever is needed to help you].
6 Yóò sì mú kí òdodo rẹ̀ jáde bí ìmọ́lẹ̀ òwúrọ̀, àti ìdájọ́ rẹ̀ bí ọ̀sán gangan.
He will show [as clearly] as the sunlight that you (are innocent/have done nothing that is wrong); he will show [as clearly] as [the sun at] noontime [SIM] that all the things that you have decided are just.
7 Ìwọ dákẹ́ jẹ́ẹ́ níwájú Olúwa, kí o sì fi sùúrù dúró dè é; má ṣe ṣe ìkanra nítorí àwọn tí ń rí rere ní ọ̀nà wọn, nítorí ọkùnrin náà ti mú èrò búburú ṣẹ.
Be quiet in Yahweh’s presence, and wait patiently for him [to do what you want him to do]. Do not be bothered/upset when what evil men do is successful, when they are able to do the wicked things that they plan.
8 Fàsẹ́yìn nínú inúbíbí, kí o sì kọ ìkáàánú sílẹ̀, má ṣe ṣe ìkanra, kí ó má ba à ṣé búburú pẹ̀lú.
Do not be angry [about what wicked people do]. Do not want to punish them yourself. Do not be envious of such people because you will only harm [yourself if you try to envy them].
9 Nítorí tí á ó gé àwọn olùṣe búburú kúrò, ṣùgbọ́n àwọn tí ó bá dúró de Olúwa àwọn ni yóò jogún ilẹ̀ náà.
[Some day Yahweh] will get rid of wicked people, but those who trust in Yahweh will live [safely] in the land [that he has given to them].
10 Síbẹ̀ nígbà díẹ̀ sí i, àwọn ènìyàn búburú kì yóò sí mọ̀; nítòótọ́ ìwọ yóò fi ara balẹ̀ wo ipò rẹ̀, wọn kì yóò sí níbẹ̀.
Soon the wicked will disappear. If you look for them, they will be gone.
11 Ṣùgbọ́n àwọn ọlọ́kàn tútù ni yóò jogún ilẹ̀ náà, wọn yóò sì máa ṣe inú dídùn nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ àlàáfíà.
But those who are humble will live safely in their land. They will happily enjoy living peacefully and having the other good things [that Yahweh gives them].
12 Ènìyàn búburú di rìkíṣí sí olóòtítọ́, wọ́n sì pa eyín wọn keke sí wọn;
Wicked people plan to harm righteous/godly people; they snarl at them [MET] [like wild animals].
13 ṣùgbọ́n Olúwa rẹ́rìn-ín sí àwọn ènìyàn búburú, nítorí tí ó rí wí pé ọjọ́ wọn ń bọ̀.
But Yahweh laughs [at them] because he knows that some day [MTY] [he will judge and punish] the wicked people.
14 Ènìyàn búburú fa idà yọ, wọ́n sì tẹ àwọn ọrun wọn, láti sọ tálákà àti aláìní kalẹ̀, láti pa àwọn tí ó dúró ṣinṣin.
Wicked people pull out their swords/daggers and they put strings on their bows, ready to kill people who are poor [DOU] and to slaughter those who live righteously.
15 Idà wọn yóò wọ àyà wọn lọ, àti wí pé ọrun wọn yóò sì ṣẹ́.
But they will be killed by their own swords/daggers, and their bows will be broken.
16 Ohun díẹ̀ tí olódodo ní, sàn ju ọ̀pọ̀ ọrọ̀ ènìyàn búburú;
It is good to be righteous/godly even if you do not have many possessions, but it is bad to be wicked, even if you are very wealthy,
17 nítorí pé a óò ṣẹ́ ọwọ́ àwọn ènìyàn búburú, ṣùgbọ́n Olúwa gbé olódodo sókè.
because [Yahweh] will completely take away the strength of wicked people, but he will (sustain/take care of) people who live righteously.
18 Olúwa mọ àwọn ọjọ́ àwọn tó dúró ṣinṣin, àti wí pé ilẹ̀ ìní wọn yóò wà títí ayérayé.
Every day Yahweh cares about those who have not done any evil things; the things that Yahweh gives them will last forever.
19 Ojú kì yóò tì wọ́n ní àkókò ibi, àti ní ọjọ́ ìyàn, a ó tẹ́ wọn lọ́rùn.
They will survive when calamities occur; when there are famines, they will still have plenty to eat.
20 Ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn búburú yóò ṣègbé. Àwọn ọ̀tá Olúwa yóò dàbí ẹwà oko tútù; wọn fò lọ; bi èéfín ni wọn yóò fò lọ kúrò.
But wicked people will die; [just] like the beautiful wild flowers in the fields [die under the hot sun] and disappear like smoke [MET], Yahweh [will cause] his enemies to suddenly disappear.
21 Àwọn ènìyàn búburú yá, wọn kò sì san án padà, ṣùgbọ́n àwọn olódodo a máa ṣàánú, a sì máa fi fún ni;
The wicked people borrow [money], but they are not able to repay it; righteous/godly people, [in contrast, have enough money that] they can give generously [to others].
22 nítorí àwọn tí Olúwa bá bùkún ni yóò jogún ilẹ̀ náà, àwọn tí ó fi bú ni a ó gé kúrò.
Those whom Yahweh has blessed will live safely in the land that he has given to them, but he will get rid of those people whom he has cursed.
23 Ìlànà ìgbésẹ̀ ènìyàn rere wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá, o sì ṣe inú dídùn sí ọ̀nà rẹ̀;
Yahweh protects those who do what is pleasing to him, and he will enable them to walk confidently, wherever they go;
24 bí ó tilẹ̀ ṣubú a kì yóò ta á nù pátápátá, nítorí tí Olúwa di ọwọ́ rẹ̀ mú.
even if they stumble, they will not fall down, because Yahweh holds them by his hand.
25 Èmi ti wà ni èwe, báyìí èmi sì dàgbà; síbẹ̀ èmi kò ì tí ì ri kí a kọ olódodo sílẹ̀, tàbí kí irú-ọmọ rẹ̀ máa ṣagbe oúnjẹ.
I was young [previously], and now I am an old man, but [in all those years], I have never seen righteous/godly people being abandoned by Yahweh, nor have I seen that their children [needed to] beg for food.
26 Aláàánú ni òun nígbà gbogbo a máa yá ni; a sì máa bùsi i fún ni.
Righteous/Godly people are generous, and happily lend [money to others], and their children are a blessing to them.
27 Lọ kúrò nínú ibi, kí o sì máa ṣe rere; nígbà náà ni ìwọ yóò gbé ní ilẹ̀ náà títí láéláé.
Turn away from [doing] evil, and do what is good. If you do that, you [and your descendants] will live in your land forever.
28 Nítorí pé Olúwa fẹ́ràn ìdájọ́ òtítọ́, kò sì kọ àwọn ènìyàn mímọ́ rẹ̀ sílẹ̀. Àwọn olódodo ni a ó pamọ́ títí ayérayé, ṣùgbọ́n àwọn ọmọ ènìyàn búburú ni a ó ké kúrò.
[That will happen] because Yahweh likes to see people doing what is just, and he will never forsake righteous/godly people. He will protect them forever; but he will get rid of the children of wicked people.
29 Olódodo ni yóò jogún ilẹ̀ náà, yóò sì máa gbé ibẹ̀ títí ayérayé.
Righteous/Godly people will own the land [that Yahweh promised to give to them], and they will live there forever.
30 Ẹnu olódodo sọ̀rọ̀ ọgbọ́n, ahọ́n rẹ̀ a sì máa sọ̀rọ̀ ìdájọ́.
Righteous people give wise [advice to others], and they [MTY] say what is just/fair.
31 Òfin Ọlọ́run rẹ̀ ń bẹ ní àyà wọn; àwọn ìgbésẹ̀ rẹ̀ kì yóò yẹ̀.
They continually think about God’s laws; they do not stray from [God’s] path.
32 Ènìyàn búburú ń ṣọ́ olódodo, Ó sì ń wá ọ̀nà láti pa á.
Those who are evil wait in ambush for righteous people in order to kill them [as they walk by].
33 Olúwa kì yóò fi lé e lọ́wọ́ kì yóò sì dá a lẹ́bi, nígbà tí a bá ń ṣe ìdájọ́ rẹ̀.
But Yahweh will not abandon righteous people, and allow (them to fall into their enemies’ hands/their enemies harm them). And he will not allow righteous people to be condemned when someone takes them to a judge [to be put on trial].
34 Dúró de Olúwa, kí o sì máa pa ọ̀nà rẹ̀ mọ́. Yóò sì gbé ọ lékè láti jogún ilẹ̀ náà; nígbà tí a bá gé àwọn ènìyàn búburú kúrò ìwọ yóò ri.
Be patient and trust that Yahweh [will help you], and (walk on his paths/do what he wants you to do). [If you do that], he will honor you by giving you the land [that he promised], and when he gets rid of the wicked, you will see it happen.
35 Èmi ti rí ènìyàn búburú tí ń hu ìwà ìkà, ó sì fi ara rẹ̀ gbilẹ̀ bí igi tútù ńlá,
I have seen that wicked people who (act like tyrants/terrify people) [sometimes] prosper, like trees that grow well in fertile soil,
36 ṣùgbọ́n ní ìṣẹ́jú kan sí i ó kọjá lọ, sì kíyèsi, kò sì sí mọ́; bi ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé mo wá a kiri, ṣùgbọ́n a kò le è ri.
when I looked [later], they were gone! I searched for them, but [Yahweh had caused] them to disappear.
37 Máa kíyèsi ẹni pípé, kí o sì wo ẹni tó dúró ṣinṣin; nítorí àlàáfíà ni òpin ọkùnrin náà.
Notice the people who have not done evil things, those who act righteously: their descendants will have peace in their inner beings.
38 Ṣùgbọ́n àwọn olùrékọjá ni a ó parun papọ̀; ìran àwọn ènìyàn búburú ni a ó gé kúrò.
But Yahweh will get rid of the wicked; he will also get rid of their descendants (OR, as a result, they will not have any descendants).
39 Ìgbàlà àwọn onídùúró ṣinṣin wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa; òun ni ààbò wọn ní ìgbà ìpọ́njú
Yahweh rescues righteous people; in times of trouble he protects them [MET].
40 Olúwa yóò ràn wọ́n lọ́wọ́ yóò sì gbà wọ́n; yóò gbà wọ́n lọ́wọ́ ènìyàn búburú, yóò sì gbà wọ́n là, nítorí tí wọ́n gbẹ́kẹ̀lé e.
Yahweh helps them and saves them; he rescues them from [being attacked/harmed by] wicked people because they go to him to be protected [MET].