< Psalms 36 >

1 Fún adarí orin. Ti Dafidi ìránṣẹ́ Olúwa. Ìré-òfin-kọjá ènìyàn búburú jẹ́ kí n mọ̀ nínú ọkàn mi pé, ìbẹ̀rù Ọlọ́run kò sí níwájú wọn.
Pour la fin, au serviteur du Seigneur, par David lui-même. L’impie a dit en lui-même qu’il pécherait: la crainte de Dieu n’est pas devant ses yeux.
2 Nítorí pé wọ́n pọ́n ara wọn ní ojú ara wọn títí tí a kò fi le rí ẹ̀ṣẹ̀ wọn láti kórìíra.
Parce qu’il a agi astucieusement en sa présence, en sorte que son iniquité est trouvée digne de haine.
3 Ọ̀rọ̀ ẹnu wọn ni ẹ̀ṣẹ̀ òhun ẹ̀tàn; wọ́n ti fi ọgbọ́n àti ṣíṣe rere sílẹ̀.
Les paroles de sa bouche sont injustice et astuce: il n’a pas voulu s’instruire pour faire le bien.
4 Wọ́n gbìmọ̀ ìwà ìkà nígbà tí wọ́n wà lórí ibùsùn wọn: wọ́n gba ọ̀nà tí kò dára wọn kò sì kọ ọ̀nà ibi sílẹ̀.
Il a médité l’iniquité sur son lit: il s’est arrêté dans toute voie qui n’était pas bonne: et la malice, il ne l’a point haïe.
5 Ìdúró ṣinṣin ìfẹ́ rẹ, ìwọ Olúwa, ó ga dé ọ̀run, òtítọ́ ọ̀ rẹ ga dé àwọsánmọ̀.
Seigneur, dans le ciel est votre miséricorde; et votre vérité s’élève jusqu’aux nues.
6 Òdodo rẹ dàbí àwọn òkè Ọlọ́run, àwọn ìdájọ́ rẹ dàbí ibú ńlá; ìwọ gba ẹranko àti ènìyàn là, Olúwa.
Votre justice est comme les montagnes de Dieu, vos jugements sont un abîme profond. Vous sauverez, Seigneur, les hommes et les animaux,
7 Báwo ni ìṣeun ìdúró ṣinṣin ìfẹ́ rẹ ti tó! Ọlọ́run! Kí gbogbo ọmọ ènìyàn le sá sí abẹ́ òjìji ìyẹ́ rẹ.
Puisque vous avez, ô Dieu, multiplié votre miséricorde. Mais les enfants des hommes espéreront à l’abri de vos ailes.
8 Àsè ilé rẹ yóò tẹ́ wọn lọ́rùn gidigidi; ìwọ yóò sì mú wọn mu nínú odò inú dídùn rẹ.
Ils seront enivrés de l’abondance de votre maison: et vous les abreuverez du torrent de vos délices.
9 Nítorí pé pẹ̀lú rẹ ni orísun ìyè wà: nínú ìmọ́lẹ̀ rẹ ni àwa yóò rí ìmọ́lẹ̀.
Parce qu’en vous est une source de vie, et que dans votre lumière nous verrons la lumière.
10 Mú ìṣeun ìfẹ́ ẹ̀ rẹ sí àwọn tí ó mọ̀ ọ́n àti ìgbàlà rẹ sí àwọn tí ó ní ìdúró ṣinṣin ọkàn!
Étendez votre miséricorde à ceux qui vous connaissent, et votre justice à ceux qui ont le cœur droit.
11 Má ṣe jẹ́ kí ẹsẹ̀ agbéraga kí ó wá sí orí mi, kí o má sì jẹ́ kí ọwọ́ àwọn ènìyàn búburú sí mi ní ipò.
Qu’un pied de superbe ne vienne pas jusqu’à moi; et qu’une main de pécheur ne m’ébranle point.
12 Níbẹ̀ ni àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ gbé ṣubú sí: a rẹ̀ wọ́n sílẹ̀, wọn kì yóò le è dìde!
Là sont tombés ceux qui opèrent l’iniquité; ils ont été chassés et n’ont pu se soutenir.

< Psalms 36 >