< Psalms 35 >

1 Ti Dafidi. Olúwa, gbógun ti àwọn tí ń gbóguntì mí; kí o sì kọ ojú ìjà sí àwọn tí ó ń bá mi í jà!
De David. Éternel, sois l'adversaire de mes adversaires; Combats ceux qui me combattent!
2 Di asà àti àpáta mú, kí o sì dìde fún ìrànlọ́wọ́ mi!
Prends le petit et le grand bouclier. Et lève-toi pour me secourir!
3 Fa idà àti ọ̀kọ̀ yọ kí o sì dojúkọ àwọn tí ń lé mi. Sọ fún ọkàn mi pé, “Èmi ni ìgbàlà rẹ.”
Brandis ta lance, barre le passage à ceux qui me poursuivent; Dis à mon âme: «Je suis ton salut!»
4 Kí wọn kí ó dààmú, kí a sì ti àwọn tí ń lépa ọkàn mi lójú; kí a sì mú wọn padà, kí a sì dààmú àwọn tí ń gbèrò ìpalára mi.
Qu'ils soient honteux et confus, ceux qui en veulent à ma vie; Qu'ils reculent et qu'ils rougissent, ceux qui méditent ma perte!
5 Jẹ́ kí wọn dàbí ìyàngbò níwájú afẹ́fẹ́, kí angẹli Olúwa kí ó máa lé wọn kiri.
Qu'ils soient comme la paille emportée par le vent. Et que l'ange de l'Éternel les chasse devant lui!
6 Jẹ́ kí ọ̀nà wọn kí ó ṣókùnkùn, kí ó sì máa yọ́, kí angẹli Olúwa kí ó máa lépa wọn!
Que leur chemin soit ténébreux et glissant. Et que l'ange de l'Éternel les poursuive!
7 Nítorí pé, ní àìnídìí ni wọ́n dẹ àwọ̀n wọn sílẹ̀ fún mi, ní àìnídìí ni wọ́n wa kòtò sílẹ̀ fún ọkàn mi.
Car, sans motif, ils ont caché leur filet sous mes pas; Sans motif, ils ont creusé une fosse pour m'ôter la vie.
8 Kí ìparun kí ó wá sí orí rẹ̀ ní òjijì. Àwọ̀n rẹ̀ tí ó dẹ, kí ó mú òun tìkára rẹ̀; kí wọn ṣubú sínú kòtò sí ìparun ara rẹ̀.
Qu'une ruine imprévue les atteigne! Qu'ils soient pris dans le filet qu'ils ont caché! Qu'ils y tombent, et qu'ils périssent!
9 Nígbà náà ni ọkàn mi yóò yọ̀ nínú Olúwa, àní, yóò sì máa yọ̀ nínú ìgbàlà rẹ̀.
Alors mon âme frémira d'allégresse en l'Éternel, Et elle se réjouira de son salut.
10 Gbogbo egungun mi yóò wí pé, “Ta ni ó dàbí ì ìwọ Olúwa? O gba tálákà lọ́wọ́ àwọn tí ó lágbára jù ú lọ, tálákà àti aláìní lọ́wọ́ ẹni tí ń fi ṣe ìkógun?”
Tous mes os diront: «Éternel, qui est semblable à toi, Toi qui délivres le malheureux du puissant qui l'opprime, Le malheureux et le pauvre de celui qui les dépouille?»
11 Àwọn ẹlẹ́rìí èké dìde; wọ́n ń bi mi ní ohun tí èmi kò mọ̀.
Des témoins criminels se lèvent; Ils m'accusent de fautes que j'ignore.
12 Wọ́n fi búburú san ìre fún mi; láti sọ ọkàn mi di òfo.
Ils me rendent le mal pour le bien; Mon âme est dans l'abandon.
13 Ṣùgbọ́n bí ó ṣe ti èmi ni, nígbà tí wọn ń ṣe àìsàn, mo wọ aṣọ ọ̀fọ̀; mo fi àwẹ̀ pọ́n ara mi lójú. Mo gba àdúrà pẹ̀lú ìtẹríba ní oókan àyà mi;
Mais moi, quand ils étaient malades, je me couvrais d'un sac. J'affligeais mon âme par le jeûne, Et je priais, la tête penchée sur ma poitrine.
14 èmí ń lọ kiri bí ẹni ń ṣọ̀fọ̀ bí i ẹni wí pé fún ọ̀rẹ́ tàbí ẹ̀gbọ́n mi ni. Èmí tẹríba nínú ìbànújẹ́ bí ẹni tí ń ṣọ̀fọ̀ ìyà rẹ̀.
Je marchais lentement. Comme si j'avais perdu un ami, un frère; J'allais en habits de deuil, Comme accablé par la mort d'une mère.
15 Ṣùgbọ́n nínú ìkọ̀sẹ̀ mi wọ́n sì yọ̀, wọ́n sì kó ara wọn jọ; wọ́n kó ara wọn jọ sí mi; àní àwọn tí èmi kò mọ̀. Wọ́n fà mí ya wọ́n kò sì dákẹ́.
Mais, si je viens à chanceler, Ils se rassemblent pour se réjouir. Ils se rassemblent contre moi, ils me calomnient à mon insu; Ils me déchirent sans relâche.
16 Bí àwọn àgàbàgebè tí ń ṣe ẹlẹ́yà ní àpèjẹ wọ́n pa eyín wọn keke sí mi.
Pareils à d'impurs bouffons de table, Ils grincent des dents contre moi.
17 Yóò ti pẹ́ tó Olúwa, tí ìwọ yóò máa wò wọ́n lọ? Yọ mí kúrò nínú ìparun wọn, àní ẹ̀mí ì mi kúrò lọ́wọ́ kìnnìún.
Seigneur, jusques à quand supporteras-tu ce spectacle? Délivre mon âme de leurs violences; Arrache ma vie à ces lions!
18 Nígbà náà ni èmi yóò ṣọpẹ́ fún Ọ nínú àjọ ńlá; èmi yóò máa yìn Ọ́ ní àwùjọ ọ̀pọ̀ ènìyàn.
Alors je te célébrerai dans la grande assemblée; Je te louerai au milieu d'un peuple nombreux.
19 Má ṣe jẹ́ kí àwọn ọ̀tá mi kí ó yọ̀ lórí ì mi; bẹ́ẹ̀ ni kí o má ṣe àwọn tí ó kórìíra mi ní àìnídìí máa ṣẹ́jú sí mi.
Puissent mes perfides ennemis N'avoir pas à se réjouir de mon sort! Que ceux qui me haïssent sans motif Ne me lancent pas des regards méprisants!
20 Nítorí pé wọn kò sọ ọ̀rọ̀ àlàáfíà, ṣùgbọ́n wọ́n lóyún ọ̀rọ̀ ẹ̀tàn sí àwọn ènìyàn dídákẹ́ ilẹ̀ náà.
Car jamais ils ne prononcent des paroles de paix; Mais ils trament de noirs complots Contre les gens tranquilles du pays.
21 Wọ́n ya ẹnu wọn gbòòrò sí mi; wọ́n wí pé, “Háà! Háà! Ojú wa sì ti rí i.”
Ils ouvrent toute grande leur bouche contre moi, Disant: «Ah! ah! Notre oeil l'a vu!» —
22 Ìwọ́ ti rí i Olúwa; má ṣe dákẹ́! Olúwa má ṣe jìnnà sí mi!
Tu l'as vu, toi aussi, ô Éternel; ne te tais point! Seigneur, ne t'éloigne point de moi!
23 Dìde! ru ara rẹ̀ sókè fún ààbò mi, àti sí ọ̀ràn mi, Ọlọ́run mi àti Olúwa mi!
Réveille-toi, lève-toi, ô mon Dieu, mon Seigneur, Pour me rendre justice, pour défendre ma cause!
24 Ṣe ìdájọ́ mi, Olúwa Ọlọ́run mi, gẹ́gẹ́ bí òdodo rẹ, kí o má sì ṣe jẹ́ kí wọn kí ó yọ̀ lórí mi!
Juge-moi selon la justice, ô Éternel, mon Dieu, Et qu'ils ne se réjouissent pas à mon sujet!
25 Má ṣe jẹ́ kí wọn wí nínú ara wọn pé, “Háà! A ti rí ohun tí ọkàn wa ń fẹ́!” Má ṣe jẹ́ kí wọn kí ó wí pé, “A ti gbé e mì.”
Qu'ils ne disent pas en leur coeur: «Ah! voilà ce que nous désirions!» Qu'ils ne puissent pas dire: «Nous l'avons anéanti!»
26 Kí ojú kí ó tì wọ́n, kí wọn kí ó sì dààmú pọ̀, àní àwọn tí ń yọ̀ sí ìyọnu mi kí a fi ìtìjú àti àbùkù wọ̀ wọ́n ní aṣọ tí ń gbéraga sí mi.
Qu'ils soient honteux et qu'ils rougissent. Tous ceux qui se réjouissent de mon malheur! Qu'ils soient couverts d'opprobre et d'infamie, Ceux qui s'élèvent orgueilleusement contre moi!
27 Jẹ́ kí àwọn tí ó fẹ́ ìdáláre mi fò fún ayọ̀ àti ìdùnnú; kí wọn máa sọ ọ́ títí lọ, “Pé gbígbéga ni Olúwa, sí àlàáfíà ìránṣẹ́ rẹ̀.”
Puissent-ils chanter et se réjouir, Ceux qui souhaitent le triomphe de ma juste cause, Et puissent-ils dire sans cesse: «Gloire soit à l'Éternel, Qui veut le bien de son serviteur!»
28 Nígbà náà ni ahọ́n mi yóò máa sọ̀rọ̀ òdodo rẹ, àti ìyìn rẹ ní gbogbo ọjọ́.
Alors ma langue proclamera ta justice, Et tous les jours elle redira tes louanges.

< Psalms 35 >