< Psalms 34 >

1 Tí Dafidi. Nígbà tí ó díbọ́n bí ẹni tí ń ṣe wèrè níwájú Abimeleki, ẹni tí ó lé e lọ, ó sì jáde lọ. Èmi yóò máa fi ìbùkún fún Olúwa nígbà gbogbo; ìyìn rẹ̀ yóò máa wà ní ẹnu mi títí láé.
Un psalm al lui David, când și-a schimbat purtarea față de Abimelec, care l-a alungat, iar el a plecat. Voi binecuvânta pe DOMNUL întotdeauna, lauda lui va fi continuu în gura mea.
2 Ọkàn mí yóò máa ṣògo nínú Olúwa; jẹ́ kí àwọn onírẹ̀lẹ̀ gbọ́ kí inú wọn kí ó sì máa dùn.
Sufletul meu se va făli în DOMNUL, cei umili vor asculta și se vor veseli.
3 Gbé Olúwa ga pẹ̀lú mi; kí ẹ sì jẹ́ kí a jọ gbé orúkọ rẹ̀ lékè.
Preamăriți pe DOMNUL împreună cu mine, și împreună să înălțăm numele lui.
4 Èmi wá Olúwa, ó sì dá mi lóhùn; Ó sì gbà mí kúrò nínú ìbẹ̀rù mi gbogbo.
Am căutat pe DOMNUL și el m-a ascultat și m-a eliberat de toate temerile mele.
5 Wọ́n wò ó, ìmọ́lẹ̀ sì mọ́ wọn; ojú kò sì tì wọ́n.
Ei au privit către el și au fost luminați, și fețele lor nu au fost făcute de rușine.
6 Ọkùnrin olùpọ́njú yí kígbe, Olúwa sì gbóhùn rẹ̀; ó sì gbà á là kúrò nínú gbogbo ìpọ́njú rẹ̀.
Săracul a strigat și DOMNUL l-a ascultat și l-a salvat din toate tulburările lui.
7 Angẹli Olúwa yí àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀ ká ó sì gbà wọ́n.
Îngerul DOMNULUI își așază tabăra de jur împrejurul celor ce se tem de el și îi eliberează.
8 Tọ́ ọ wò kí o sì rí i wí pé Olúwa dára; ẹni ayọ̀ ni ọkùnrin náà tí ó gbẹ́kẹ̀lé ààbò nínú rẹ̀.
Gustați și vedeți că DOMNUL este bun; binecuvântat este omul care se încrede în el.
9 Ẹ bẹ̀rù Olúwa, ẹ̀yin ènìyàn rẹ̀ mímọ́, nítorí pé kò sí àìní fún àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀.
Temeți-vă de DOMNUL, voi sfinții lui, pentru că nimic nu le lipsește celor ce se tem de el.
10 Àwọn ọmọ kìnnìún a máa ṣe aláìní ebi a sì máa pa wọ́n; ṣùgbọ́n àwọn tí ó wá Olúwa kì yóò ṣe aláìní ohun tí ó dára.
Leii tineri duc lipsă și le este foame, dar cei ce caută pe DOMNUL nu vor duce lipsă de niciun bine.
11 Wá, ẹ̀yin ọmọ mi, fi etí sí mi; èmi yóò kọ́ ọ yín ní ẹ̀rù Olúwa.
Veniți, voi copii, dați-mi ascultare, vă voi învăța teama de DOMNUL.
12 Ta ni nínú yín tí ń fẹ́ ìyè, tí ó sì ń fẹ́ ọjọ́ púpọ̀; kí ó lè gbádùn ọjọ́ rere?
Cine este omul care dorește viața și iubește zile multe, ca să vadă binele?
13 Pa ahọ́n rẹ̀ mọ́ kúrò nínú ibi àti ètè rẹ̀ kúrò ní ẹ̀tàn sísọ.
Păzește-ți limba de la rău, și buzele tale de la a vorbi viclenie.
14 Yà kúrò nínú ibi kí o sì ṣe rere; wá àlàáfíà, kí o sì lépa rẹ̀.
Pleacă de la rău și fă binele; caută pacea și urmărește-o.
15 Ojú Olúwa ń bẹ lára àwọn olódodo; etí i rẹ̀ sì ṣí sí ẹkún wọn.
Ochii DOMNULUI sunt peste cei drepți și urechile lui sunt deschise la strigătul lor.
16 Ojú Olúwa korò sí àwọn tí ń ṣe búburú; láti ké ìrántí wọn kúrò lórí ilẹ̀.
Fața DOMNULUI este împotriva celor ce fac răul, pentru a stârpi amintirea lor de pe pământ.
17 Nígbà tí olódodo bá ké fún ìrànlọ́wọ́, Olúwa a máa gbọ́, a sì yọ wọ́n jáde láti inú gbogbo wàhálà wọn.
Cei drepți strigă și DOMNUL ascultă și îi eliberează din toate tulburările lor.
18 Olúwa súnmọ́ etí ọ̀dọ̀ àwọn oníròbìnújẹ́ ọkàn; ó sì gba irú àwọn tí í ṣe oníròra ọkàn là.
DOMNUL este aproape de cei cu o inimă frântă și salvează pe cei cu un duh căit.
19 Ìpọ́njú àwọn olódodo pọ̀, ṣùgbọ́n Olúwa gbà wọ́n kúrò nínú gbogbo rẹ̀.
Multe sunt nenorocirile celui drept, dar DOMNUL îl eliberează din toate.
20 Ó pa gbogbo egungun wọn mọ́; kò sí ọ̀kan tí ó dá nínú wọn.
El păzește toate oasele lui, niciunul din ele nu este frânt.
21 Ibi ni ó mú ikú ìkà wá, àti àwọn tí ó kórìíra olódodo ni yóò jẹ̀bi.
Răul îl va ucide pe cel stricat și cei ce urăsc pe cel drept vor fi pustiiți.
22 Olúwa ra ọkàn àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ padà; kò sí ọ̀kan nínú àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé tí yóò jẹ̀bi.
DOMNUL răscumpără sufletul servitorilor săi și niciunul dintre cei ce se încred în el nu va fi pustiit.

< Psalms 34 >