< Psalms 34 >

1 Tí Dafidi. Nígbà tí ó díbọ́n bí ẹni tí ń ṣe wèrè níwájú Abimeleki, ẹni tí ó lé e lọ, ó sì jáde lọ. Èmi yóò máa fi ìbùkún fún Olúwa nígbà gbogbo; ìyìn rẹ̀ yóò máa wà ní ẹnu mi títí láé.
Psalm Dawida, gdy zmienił swoje zachowanie przed Abimelekiem i wypędzony przez niego, odszedł. Będę błogosławił PANA w każdym czasie, jego chwała zawsze [będzie] na moich ustach.
2 Ọkàn mí yóò máa ṣògo nínú Olúwa; jẹ́ kí àwọn onírẹ̀lẹ̀ gbọ́ kí inú wọn kí ó sì máa dùn.
Moja dusza będzie się chlubić PANEM; pokorni [to] usłyszą i rozradują się.
3 Gbé Olúwa ga pẹ̀lú mi; kí ẹ sì jẹ́ kí a jọ gbé orúkọ rẹ̀ lékè.
Uwielbiajcie PANA ze mną i wspólnie wywyższajmy jego imię.
4 Èmi wá Olúwa, ó sì dá mi lóhùn; Ó sì gbà mí kúrò nínú ìbẹ̀rù mi gbogbo.
Szukałem PANA, a on mnie wysłuchał i uwolnił od wszystkich mych trwóg.
5 Wọ́n wò ó, ìmọ́lẹ̀ sì mọ́ wọn; ojú kò sì tì wọ́n.
Spojrzeli na niego i rozpromienili się, a ich oblicza nie doznały wstydu.
6 Ọkùnrin olùpọ́njú yí kígbe, Olúwa sì gbóhùn rẹ̀; ó sì gbà á là kúrò nínú gbogbo ìpọ́njú rẹ̀.
Ten oto biedak wołał, a PAN wysłuchał i wybawił go ze wszystkich jego utrapień.
7 Angẹli Olúwa yí àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀ ká ó sì gbà wọ́n.
Anioł PANA rozbija obóz dokoła tych, którzy się go boją, i wybawia ich.
8 Tọ́ ọ wò kí o sì rí i wí pé Olúwa dára; ẹni ayọ̀ ni ọkùnrin náà tí ó gbẹ́kẹ̀lé ààbò nínú rẹ̀.
Skosztujcie i zobaczcie, jak dobry jest PAN: Błogosławiony człowiek, który mu ufa.
9 Ẹ bẹ̀rù Olúwa, ẹ̀yin ènìyàn rẹ̀ mímọ́, nítorí pé kò sí àìní fún àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀.
Bójcie się PANA, jego święci, bo niczego nie braknie tym, którzy się go boją.
10 Àwọn ọmọ kìnnìún a máa ṣe aláìní ebi a sì máa pa wọ́n; ṣùgbọ́n àwọn tí ó wá Olúwa kì yóò ṣe aláìní ohun tí ó dára.
Lwięta cierpią niedostatek i głód, lecz szukającym PANA nie zabraknie żadnego dobra.
11 Wá, ẹ̀yin ọmọ mi, fi etí sí mi; èmi yóò kọ́ ọ yín ní ẹ̀rù Olúwa.
Chodźcie, synowie, słuchajcie mnie; nauczę was bojaźni PANA.
12 Ta ni nínú yín tí ń fẹ́ ìyè, tí ó sì ń fẹ́ ọjọ́ púpọ̀; kí ó lè gbádùn ọjọ́ rere?
Który człowiek chce [długo] żyć i pragnie [wiele] dni, aby móc oglądać dobro?
13 Pa ahọ́n rẹ̀ mọ́ kúrò nínú ibi àti ètè rẹ̀ kúrò ní ẹ̀tàn sísọ.
Strzeż swego języka od zła, a swoich warg od podstępnej mowy.
14 Yà kúrò nínú ibi kí o sì ṣe rere; wá àlàáfíà, kí o sì lépa rẹ̀.
Odwróć się od zła i czyń dobrze, szukaj pokoju i dąż do niego.
15 Ojú Olúwa ń bẹ lára àwọn olódodo; etí i rẹ̀ sì ṣí sí ẹkún wọn.
Oczy PANA [są zwrócone] na sprawiedliwych, a jego uszy [nachylone] na ich wołanie;
16 Ojú Olúwa korò sí àwọn tí ń ṣe búburú; láti ké ìrántí wọn kúrò lórí ilẹ̀.
[Lecz] oblicze PANA [jest] przeciwko złoczyńcom, aby pamięć o nich wymazać z ziemi.
17 Nígbà tí olódodo bá ké fún ìrànlọ́wọ́, Olúwa a máa gbọ́, a sì yọ wọ́n jáde láti inú gbogbo wàhálà wọn.
Wołają [sprawiedliwi], a PAN wysłuchuje ich i uwalnia od wszelkich trudności.
18 Olúwa súnmọ́ etí ọ̀dọ̀ àwọn oníròbìnújẹ́ ọkàn; ó sì gba irú àwọn tí í ṣe oníròra ọkàn là.
Bliski [jest] PAN skruszonym w sercu i wybawia złamanych na duchu.
19 Ìpọ́njú àwọn olódodo pọ̀, ṣùgbọ́n Olúwa gbà wọ́n kúrò nínú gbogbo rẹ̀.
Liczne [są] cierpienia sprawiedliwego, ale PAN uwalnia go od nich wszystkich.
20 Ó pa gbogbo egungun wọn mọ́; kò sí ọ̀kan tí ó dá nínú wọn.
On strzeże wszystkich jego kości; ani jedna z nich nie będzie złamana.
21 Ibi ni ó mú ikú ìkà wá, àti àwọn tí ó kórìíra olódodo ni yóò jẹ̀bi.
Zło zabija niegodziwego i ci, którzy nienawidzą sprawiedliwego, będą zniszczeni;
22 Olúwa ra ọkàn àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ padà; kò sí ọ̀kan nínú àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé tí yóò jẹ̀bi.
PAN odkupi dusze swoich sług i nie będą zniszczeni ci, którzy mu ufają.

< Psalms 34 >