< Psalms 34 >

1 Tí Dafidi. Nígbà tí ó díbọ́n bí ẹni tí ń ṣe wèrè níwájú Abimeleki, ẹni tí ó lé e lọ, ó sì jáde lọ. Èmi yóò máa fi ìbùkún fún Olúwa nígbà gbogbo; ìyìn rẹ̀ yóò máa wà ní ẹnu mi títí láé.
Psalm Dawidowy, gdy sobie odmienił postawę przed Abimelechem, od którego będąc wygnany, odszedł. Będę błogosławił Pana na każdy czas; zawżdy będzie chwała jego w ustach moich.
2 Ọkàn mí yóò máa ṣògo nínú Olúwa; jẹ́ kí àwọn onírẹ̀lẹ̀ gbọ́ kí inú wọn kí ó sì máa dùn.
W Panu się chlubić będzie dusza moja, co usłyszawszy pokorni rozweselą się.
3 Gbé Olúwa ga pẹ̀lú mi; kí ẹ sì jẹ́ kí a jọ gbé orúkọ rẹ̀ lékè.
Wielbijcie Pana ze mną, a wywyższajmy imię jego społecznie.
4 Èmi wá Olúwa, ó sì dá mi lóhùn; Ó sì gbà mí kúrò nínú ìbẹ̀rù mi gbogbo.
Bom szukał Pana, i wysłuchał mię, a ze wszystkich strachów moich wyrwał mię.
5 Wọ́n wò ó, ìmọ́lẹ̀ sì mọ́ wọn; ojú kò sì tì wọ́n.
Którzy nań spoglądają, a zbiegają się do niego, oblicza ich nie będą zawstydzone.
6 Ọkùnrin olùpọ́njú yí kígbe, Olúwa sì gbóhùn rẹ̀; ó sì gbà á là kúrò nínú gbogbo ìpọ́njú rẹ̀.
Ten chudzina wołał, a Pan wysłuchał, i ze wszystkich ucisków jego wybawił go.
7 Angẹli Olúwa yí àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀ ká ó sì gbà wọ́n.
Zatacza obóz Anioł Pański około tych, którzy się go boją, i wyrywa ich.
8 Tọ́ ọ wò kí o sì rí i wí pé Olúwa dára; ẹni ayọ̀ ni ọkùnrin náà tí ó gbẹ́kẹ̀lé ààbò nínú rẹ̀.
Skosztujcież, a obaczcie, jako jest dobry Pan: błogosławiony człowiek, który w nim ufa.
9 Ẹ bẹ̀rù Olúwa, ẹ̀yin ènìyàn rẹ̀ mímọ́, nítorí pé kò sí àìní fún àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀.
Bójcie się Pana święci jego; bo niemasz niedostatku bojącym się go.
10 Àwọn ọmọ kìnnìún a máa ṣe aláìní ebi a sì máa pa wọ́n; ṣùgbọ́n àwọn tí ó wá Olúwa kì yóò ṣe aláìní ohun tí ó dára.
Lwięta niedostatek cierpią i głód; lecz szukającym Pana nie będzie schodziło na wszelkiem dobrem.
11 Wá, ẹ̀yin ọmọ mi, fi etí sí mi; èmi yóò kọ́ ọ yín ní ẹ̀rù Olúwa.
Pójdźcież synowie, słuchajcie mię; bojaźni Pańskiej was nauczę.
12 Ta ni nínú yín tí ń fẹ́ ìyè, tí ó sì ń fẹ́ ọjọ́ púpọ̀; kí ó lè gbádùn ọjọ́ rere?
Któż jest, co chce długo żyć, a miłuje dni, aby widział dobra?
13 Pa ahọ́n rẹ̀ mọ́ kúrò nínú ibi àti ètè rẹ̀ kúrò ní ẹ̀tàn sísọ.
Strzeż języka twego od złego, a warg twoich, aby nie mówiły zdrady.
14 Yà kúrò nínú ibi kí o sì ṣe rere; wá àlàáfíà, kí o sì lépa rẹ̀.
Odwróć się od złego, a czyń dobrze; szukaj pokoju, a ścigaj go.
15 Ojú Olúwa ń bẹ lára àwọn olódodo; etí i rẹ̀ sì ṣí sí ẹkún wọn.
Oczy Pańskie otworzone są na sprawiedliwych, a uszy jego na wołanie ich;
16 Ojú Olúwa korò sí àwọn tí ń ṣe búburú; láti ké ìrántí wọn kúrò lórí ilẹ̀.
Ale oblicze Pańskie przeciwko tym, którzy broją złości, aby wykorzenił z ziemi pamiątkę ich.
17 Nígbà tí olódodo bá ké fún ìrànlọ́wọ́, Olúwa a máa gbọ́, a sì yọ wọ́n jáde láti inú gbogbo wàhálà wọn.
Wołają sprawiedliwi, a Pan ich wysłuchiwa, i ze wszystkich trudności ich wybawia ich.
18 Olúwa súnmọ́ etí ọ̀dọ̀ àwọn oníròbìnújẹ́ ọkàn; ó sì gba irú àwọn tí í ṣe oníròra ọkàn là.
Bliski jest Pan tym, którzy są skruszonego serca, a utrapionych w duchu zachowuje.
19 Ìpọ́njú àwọn olódodo pọ̀, ṣùgbọ́n Olúwa gbà wọ́n kúrò nínú gbogbo rẹ̀.
Wiele złego przychodzi na sprawiedliwego; ale z tego wszystkiego wyrywa go Pan.
20 Ó pa gbogbo egungun wọn mọ́; kò sí ọ̀kan tí ó dá nínú wọn.
On strzeże wszystkich kości jego, tak, iż i jedna z nich nie skruszy się.
21 Ibi ni ó mú ikú ìkà wá, àti àwọn tí ó kórìíra olódodo ni yóò jẹ̀bi.
Zabije złość niepobożnego, a którzy w nienawiści mają sprawiedliwego, będą spustoszeni;
22 Olúwa ra ọkàn àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ padà; kò sí ọ̀kan nínú àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé tí yóò jẹ̀bi.
Ale Pan odkupi duszę sług swoich, a nie będą spustoszeni wszyscy, którzy w nim ufają.

< Psalms 34 >