< Psalms 34 >

1 Tí Dafidi. Nígbà tí ó díbọ́n bí ẹni tí ń ṣe wèrè níwájú Abimeleki, ẹni tí ó lé e lọ, ó sì jáde lọ. Èmi yóò máa fi ìbùkún fún Olúwa nígbà gbogbo; ìyìn rẹ̀ yóò máa wà ní ẹnu mi títí láé.
Davidův, když proměnil oblíčej svůj před Abimelechem; pročež jsa od něho vyhnán, odšel. Dobrořečiti budu Hospodinu každého času, vždycky chvála jeho v ústech mých.
2 Ọkàn mí yóò máa ṣògo nínú Olúwa; jẹ́ kí àwọn onírẹ̀lẹ̀ gbọ́ kí inú wọn kí ó sì máa dùn.
V Hospodinu chlubiti se bude duše má, což uslyšíc tiší, budou se veseliti.
3 Gbé Olúwa ga pẹ̀lú mi; kí ẹ sì jẹ́ kí a jọ gbé orúkọ rẹ̀ lékè.
Zvelebujtež se mnou Hospodina, a jméno jeho společně vyvyšujme.
4 Èmi wá Olúwa, ó sì dá mi lóhùn; Ó sì gbà mí kúrò nínú ìbẹ̀rù mi gbogbo.
Hledal jsem Hospodina, a vyslyšel mne, a ze všech přístrachů mých vytrhl mne.
5 Wọ́n wò ó, ìmọ́lẹ̀ sì mọ́ wọn; ojú kò sì tì wọ́n.
Pročež k němu patřiti budou, a sbíhati se, a nebudou zahanbeny tváři jejich, ale řkou:
6 Ọkùnrin olùpọ́njú yí kígbe, Olúwa sì gbóhùn rẹ̀; ó sì gbà á là kúrò nínú gbogbo ìpọ́njú rẹ̀.
Tento chudý volal a Hospodin vyslyšel, i ze všech úzkostí jeho vysvobodil jej.
7 Angẹli Olúwa yí àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀ ká ó sì gbà wọ́n.
Vojensky se klade anděl Hospodinův okolo těch, kteříž se ho bojí, a zastává jich.
8 Tọ́ ọ wò kí o sì rí i wí pé Olúwa dára; ẹni ayọ̀ ni ọkùnrin náà tí ó gbẹ́kẹ̀lé ààbò nínú rẹ̀.
Okuste a vizte, jak dobrý jest Hospodin. Blahoslavený člověk, kterýž doufá v něho.
9 Ẹ bẹ̀rù Olúwa, ẹ̀yin ènìyàn rẹ̀ mímọ́, nítorí pé kò sí àìní fún àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀.
Bojtež se Hospodina svatí jeho; neboť nemívají nedostatku ti, kdož se ho bojí.
10 Àwọn ọmọ kìnnìún a máa ṣe aláìní ebi a sì máa pa wọ́n; ṣùgbọ́n àwọn tí ó wá Olúwa kì yóò ṣe aláìní ohun tí ó dára.
Lvíčátka nedostatek a hlad trpívají, ale ti, kteříž hledají Hospodina, nemívají nedostatku ve všem dobrém.
11 Wá, ẹ̀yin ọmọ mi, fi etí sí mi; èmi yóò kọ́ ọ yín ní ẹ̀rù Olúwa.
Poďtež, dítky, poslouchejte mne, bázni Hospodinově vyučovati vás budu.
12 Ta ni nínú yín tí ń fẹ́ ìyè, tí ó sì ń fẹ́ ọjọ́ púpọ̀; kí ó lè gbádùn ọjọ́ rere?
Který člověk žádostiv jest života, a miluje dny, aby užíval dobrých věcí?
13 Pa ahọ́n rẹ̀ mọ́ kúrò nínú ibi àti ètè rẹ̀ kúrò ní ẹ̀tàn sísọ.
Zdržuj jazyk svůj od zlého, a rty své od mluvení lsti.
14 Yà kúrò nínú ibi kí o sì ṣe rere; wá àlàáfíà, kí o sì lépa rẹ̀.
Odstup od zlého, a čiň dobré, hledej pokoje, a stíhej jej.
15 Ojú Olúwa ń bẹ lára àwọn olódodo; etí i rẹ̀ sì ṣí sí ẹkún wọn.
Oči Hospodinovy obrácené jsou k spravedlivým, a uši jeho k volání jejich:
16 Ojú Olúwa korò sí àwọn tí ń ṣe búburú; láti ké ìrántí wọn kúrò lórí ilẹ̀.
Ale zůřivý oblíčej Hospodinův proti těm, kteříž páší zlé věci, aby vyplénil z země památku jejich.
17 Nígbà tí olódodo bá ké fún ìrànlọ́wọ́, Olúwa a máa gbọ́, a sì yọ wọ́n jáde láti inú gbogbo wàhálà wọn.
Volají-li spravedliví, Hospodin vyslýchá, a ze všech jejich úzkostí je vytrhuje.
18 Olúwa súnmọ́ etí ọ̀dọ̀ àwọn oníròbìnújẹ́ ọkàn; ó sì gba irú àwọn tí í ṣe oníròra ọkàn là.
Nebo blízko jest Hospodin těm, kteříž jsou srdce skroušeného, a potřeným v duchu spomáhá.
19 Ìpọ́njú àwọn olódodo pọ̀, ṣùgbọ́n Olúwa gbà wọ́n kúrò nínú gbogbo rẹ̀.
Mnohé úzkosti jsou spravedlivého, ale Hospodin ze všech jej vytrhuje.
20 Ó pa gbogbo egungun wọn mọ́; kò sí ọ̀kan tí ó dá nínú wọn.
Onť ostříhá všech kostí jeho, žádná z nich nebývá zlámána.
21 Ibi ni ó mú ikú ìkà wá, àti àwọn tí ó kórìíra olódodo ni yóò jẹ̀bi.
Bezbožníka zahubí zlost, a ti, kteříž nenávidí spravedlivého, zkaženi budou.
22 Olúwa ra ọkàn àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ padà; kò sí ọ̀kan nínú àwọn tí ó gbẹ́kẹ̀lé tí yóò jẹ̀bi.
Služebníků pak svých duše vykoupí Hospodin, a nebudou zkaženi, kteříž doufají v něho.

< Psalms 34 >