< Psalms 33 >

1 Ẹ yọ̀ nínú Olúwa, ẹ̀yin olódodo; ìyìn si yẹ fún ẹni dídúró ṣinṣin.
¡Que los rectos griten de alegría! ¡Que te adoren los que hacen el bien!
2 Ẹ yin Olúwa pẹ̀lú dùùrù; ẹ máa fi ohun èlò olókùn mẹ́wàá kọrin sí i.
Alaba al Señor con Lira, toca música para él con el decacordio.
3 Ẹ kọ orin tuntun sí i; ẹ máa fi ọgbọọgbọ́n lu ohun èlò orin sí i, pẹ̀lú ariwo.
Cántale nueva canción; toca bien tus instrumentos y grita de alegría.
4 Nítorí pé ọ̀rọ̀ Olúwa dúró ṣinṣin, gbogbo iṣẹ́ rẹ̀ ni à ń ṣe nínú òtítọ́.
Porque la palabra del Señor es verdadera, y él merece toda la confianza en lo que hace.
5 Ó fẹ́ òtítọ́ àti ìdájọ́; ilé ayé kún fún ìdúró ṣinṣin àti àánú Olúwa.
Él ama todo lo bueno y lo correcto; la tierra está llena del amor inefable del Señor.
6 Nípasẹ̀ ọ̀rọ̀ Olúwa ni a ṣe dá àwọn ọ̀run, àti gbogbo àwọn ẹgbẹ́ ogun wọn nípa ìmísí ẹnu rẹ̀.
El Señor habló y los cielos fueron hechos. Su boca sopló, y todas las estrellas existieron.
7 Ó kó àwọn omi òkun jọ gẹ́gẹ́ bí èyí tí ó wà nínú ìgò; ó sì fi ibú ṣe ilé ìṣúra gbogbo.
Reúne las aguas de los mares, mantiene almacenadas las profundidades del océano.
8 Jẹ́ kí gbogbo ayé kí ó bẹ̀rù Olúwa: jẹ́ kí gbogbo àwọn olùgbé ayé kí ó wà nínú ìbẹ̀rù rẹ̀.
Reverencie toda la tierra al Señor; que todos los habitantes de la tierra se maravillen con su presencia.
9 Nítorí tí ó sọ̀rọ̀, ó sì ti rí bẹ́ẹ̀; ó pàṣẹ ó sì dúró ṣinṣin.
Porque él habló, y el mundo vino a la existencia; dio la orden, y fue creado.
10 Olúwa ti mú ìmọ̀ràn àwọn orílẹ̀-èdè wá sí asán; ó sì mú àrékérekè àwọn ènìyàn di ṣíṣákì í.
El Señor frustra los planes de las naciones y de los pueblos.
11 Ìgbìmọ̀ Olúwa dúró títí ayérayé, àní ìrò inú rẹ̀ láti ìrandíran ni.
Pero el plan del Señor permanece para siempre. Sus propósitos perduran a través de las generaciones.
12 Ìbùkún ni fún orílẹ̀-èdè náà, Ọlọ́run ẹni tí Olúwa jẹ́ tirẹ̀, àti àwọn ènìyàn náà tí ó ti yàn ṣe ìní rẹ̀.
Feliz es la nación cuyo Dios es el Señor, el pueblo que ha escogido como enteramente suyo.
13 Olúwa wò láti ọ̀run wá; Ó sì rí gbogbo ìran ènìyàn.
El Señor mira desde los cielos y ve toda la humanidad,
14 Níbi tí ó ti jókòó lórí ìtẹ́ Ó wo gbogbo àwọn olùgbé ayé
desde su trono él ve a todos los que habitan en la tierra.
15 ẹni tí ó ṣe àyà wọn bákan náà, ó sì kíyèsi ìṣe wọn.
Él creó sus mentes, y reconoce todo lo que hacen.
16 A kò gba ọba kan là nípasẹ̀ ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ọmọ-ogun; kò sì sí jagunjagun tí a gbà sílẹ̀ nípa agbára ńlá rẹ̀.
Ni el más grande ejército puede salvar a un rey; ni la fuerza más poderosa puede salvar a un guerrero.
17 Ohun asán ni ẹṣin fún ìṣẹ́gun; bẹ́ẹ̀ ni kì yóò fi agbára ńlá rẹ̀ gbani sílẹ̀.
No te engañes: un caballo de guerra no puede darte la victoria, ni su increíble fuerza podrá salvarte.
18 Wò ó, ojú Olúwa wà lára àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀, àti lára àwọn tí ó ní ìrètí nínú ìfẹ́ rẹ̀ tí ó dúró ṣinṣin.
El Señor cuida de quienes lo siguen con reverencia, de los que depositan su esperanza en su amor inagotable,
19 Láti gba ọkàn wọn kúrò lọ́wọ́ ikú àti láti pa wọ́n mọ́ láààyè lọ́wọ́ ìyàn.
para que los salve de la muerte y para que los mantenga vivos cuando el hambre ataque.
20 Ọkàn wa dúró de Olúwa; òun ni ìrànlọ́wọ́ wa àti asà wa.
Ponemos nuestra confianza en el Señor. Él es nuestra ayuda y nuestro defensor.
21 Ọkàn wa yọ̀ nínú rẹ̀, nítorí pé, àwa gbẹ́kẹ̀lé orúkọ rẹ mímọ́.
Nuestros corazones están llenos de alegría, porque confiamos en su carácter santo.
22 Kí àánú rẹ, Olúwa, kí ó wà lára wa, àní gẹ́gẹ́ bí àwa ti ń ṣe ìrètí nínú rẹ.
Que tu gran amor descanse sobre nosotros mientras esperamos en ti.

< Psalms 33 >