< Psalms 33 >

1 Ẹ yọ̀ nínú Olúwa, ẹ̀yin olódodo; ìyìn si yẹ fún ẹni dídúró ṣinṣin.
Weselcie się w PANU, sprawiedliwi, [bo] prawym przystoi chwała.
2 Ẹ yin Olúwa pẹ̀lú dùùrù; ẹ máa fi ohun èlò olókùn mẹ́wàá kọrin sí i.
Wysławiajcie PANA na harfie, śpiewajcie mu przy cytrze [i] z instrumentem o dziesięciu strunach.
3 Ẹ kọ orin tuntun sí i; ẹ máa fi ọgbọọgbọ́n lu ohun èlò orin sí i, pẹ̀lú ariwo.
Śpiewajcie mu nową pieśń, pięknie i głośno mu grajcie.
4 Nítorí pé ọ̀rọ̀ Olúwa dúró ṣinṣin, gbogbo iṣẹ́ rẹ̀ ni à ń ṣe nínú òtítọ́.
Słowo PANA bowiem [jest] prawe i wszystkie jego dzieła [są dokonane w] wierności.
5 Ó fẹ́ òtítọ́ àti ìdájọ́; ilé ayé kún fún ìdúró ṣinṣin àti àánú Olúwa.
On miłuje sprawiedliwość i sąd, pełna jest ziemia miłosierdzia PANA.
6 Nípasẹ̀ ọ̀rọ̀ Olúwa ni a ṣe dá àwọn ọ̀run, àti gbogbo àwọn ẹgbẹ́ ogun wọn nípa ìmísí ẹnu rẹ̀.
Słowem PANA zostały uczynione niebiosa i tchnieniem jego ust wszystkie ich zastępy.
7 Ó kó àwọn omi òkun jọ gẹ́gẹ́ bí èyí tí ó wà nínú ìgò; ó sì fi ibú ṣe ilé ìṣúra gbogbo.
On gromadzi wody morskie jak na stos i w skarbcach zbiera głębiny.
8 Jẹ́ kí gbogbo ayé kí ó bẹ̀rù Olúwa: jẹ́ kí gbogbo àwọn olùgbé ayé kí ó wà nínú ìbẹ̀rù rẹ̀.
Niech cała ziemia boi się PANA, niech się go lękają wszyscy mieszkańcy świata.
9 Nítorí tí ó sọ̀rọ̀, ó sì ti rí bẹ́ẹ̀; ó pàṣẹ ó sì dúró ṣinṣin.
On bowiem przemówił i stało się; on rozkazał i powstało.
10 Olúwa ti mú ìmọ̀ràn àwọn orílẹ̀-èdè wá sí asán; ó sì mú àrékérekè àwọn ènìyàn di ṣíṣákì í.
PAN udaremnia zamiary narodów, niweczy zamysły ludów.
11 Ìgbìmọ̀ Olúwa dúró títí ayérayé, àní ìrò inú rẹ̀ láti ìrandíran ni.
Zamiar PANA trwa na wieki, myśli jego serca z pokolenia na pokolenie.
12 Ìbùkún ni fún orílẹ̀-èdè náà, Ọlọ́run ẹni tí Olúwa jẹ́ tirẹ̀, àti àwọn ènìyàn náà tí ó ti yàn ṣe ìní rẹ̀.
Błogosławiony naród, którego Bogiem jest PAN; lud, który on wybrał sobie na dziedzictwo.
13 Olúwa wò láti ọ̀run wá; Ó sì rí gbogbo ìran ènìyàn.
PAN patrzy z nieba, widzi wszystkich synów ludzkich.
14 Níbi tí ó ti jókòó lórí ìtẹ́ Ó wo gbogbo àwọn olùgbé ayé
Z miejsca, w którym przebywa, spogląda na wszystkich mieszkańców ziemi.
15 ẹni tí ó ṣe àyà wọn bákan náà, ó sì kíyèsi ìṣe wọn.
Ukształtował serce każdego z nich, przygląda się wszystkim ich czynom.
16 A kò gba ọba kan là nípasẹ̀ ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ọmọ-ogun; kò sì sí jagunjagun tí a gbà sílẹ̀ nípa agbára ńlá rẹ̀.
Nie wybawi króla liczne wojsko [ani] nie ocali wojownika wielka siła.
17 Ohun asán ni ẹṣin fún ìṣẹ́gun; bẹ́ẹ̀ ni kì yóò fi agbára ńlá rẹ̀ gbani sílẹ̀.
Koń jest zwodniczy w wybawieniu, nie ocali swą wielką siłą.
18 Wò ó, ojú Olúwa wà lára àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀, àti lára àwọn tí ó ní ìrètí nínú ìfẹ́ rẹ̀ tí ó dúró ṣinṣin.
Oto oko PANA nad tymi, którzy się go boją, nad tymi, którzy ufają jego miłosierdziu;
19 Láti gba ọkàn wọn kúrò lọ́wọ́ ikú àti láti pa wọ́n mọ́ láààyè lọ́wọ́ ìyàn.
Aby ocalić od śmierci ich duszę i żywić ich w czasie głodu.
20 Ọkàn wa dúró de Olúwa; òun ni ìrànlọ́wọ́ wa àti asà wa.
Nasza dusza oczekuje PANA, on [jest] naszą pomocą i tarczą.
21 Ọkàn wa yọ̀ nínú rẹ̀, nítorí pé, àwa gbẹ́kẹ̀lé orúkọ rẹ mímọ́.
W nim bowiem rozraduje się nasze serce, bo ufamy jego świętemu imieniu.
22 Kí àánú rẹ, Olúwa, kí ó wà lára wa, àní gẹ́gẹ́ bí àwa ti ń ṣe ìrètí nínú rẹ.
Niech będzie nad nami twoje miłosierdzie, PANIE, według pokładanej w tobie nadziei.

< Psalms 33 >