< Psalms 33 >

1 Ẹ yọ̀ nínú Olúwa, ẹ̀yin olódodo; ìyìn si yẹ fún ẹni dídúró ṣinṣin.
Weselcie się w Panu sprawiedliwi; bo szczerym przystoi chwalić Pana.
2 Ẹ yin Olúwa pẹ̀lú dùùrù; ẹ máa fi ohun èlò olókùn mẹ́wàá kọrin sí i.
Wysławiajcie Pana na harfie, na lutni, na instrumencie o dziesięciu stronach, śpiewajcie mu.
3 Ẹ kọ orin tuntun sí i; ẹ máa fi ọgbọọgbọ́n lu ohun èlò orin sí i, pẹ̀lú ariwo.
Śpiewajcież mu piosnkę nową; dobrze mu i głośno grajcie.
4 Nítorí pé ọ̀rọ̀ Olúwa dúró ṣinṣin, gbogbo iṣẹ́ rẹ̀ ni à ń ṣe nínú òtítọ́.
Albowiem szczere jest słowo Pańskie, i wszystkie sprawy jego wierne.
5 Ó fẹ́ òtítọ́ àti ìdájọ́; ilé ayé kún fún ìdúró ṣinṣin àti àánú Olúwa.
Miłuje sąd i sprawiedliwość; pełna jest ziemia miłosierdzia Pańskiego.
6 Nípasẹ̀ ọ̀rọ̀ Olúwa ni a ṣe dá àwọn ọ̀run, àti gbogbo àwọn ẹgbẹ́ ogun wọn nípa ìmísí ẹnu rẹ̀.
Słowem Pańskiem są niebiosa uczynione, a Duchem ust jego wszystko wojsko ich.
7 Ó kó àwọn omi òkun jọ gẹ́gẹ́ bí èyí tí ó wà nínú ìgò; ó sì fi ibú ṣe ilé ìṣúra gbogbo.
Który zgromadził jako na kupę wody morskie, i złożył do skarbu przepaści.
8 Jẹ́ kí gbogbo ayé kí ó bẹ̀rù Olúwa: jẹ́ kí gbogbo àwọn olùgbé ayé kí ó wà nínú ìbẹ̀rù rẹ̀.
Niech się boi Pana wszystka ziemia; niech się go lękają wszyscy obywatele okręgu ziemi.
9 Nítorí tí ó sọ̀rọ̀, ó sì ti rí bẹ́ẹ̀; ó pàṣẹ ó sì dúró ṣinṣin.
Albowiem on rzekł, i stało się; on rozkazał, a stanęło.
10 Olúwa ti mú ìmọ̀ràn àwọn orílẹ̀-èdè wá sí asán; ó sì mú àrékérekè àwọn ènìyàn di ṣíṣákì í.
Pan rozprasza rady narodów, a wniwecz obraca zamysły ludzkie;
11 Ìgbìmọ̀ Olúwa dúró títí ayérayé, àní ìrò inú rẹ̀ láti ìrandíran ni.
Ale rada Pańska trwa na wieki, a myśli serca jego od narodu do narodu.
12 Ìbùkún ni fún orílẹ̀-èdè náà, Ọlọ́run ẹni tí Olúwa jẹ́ tirẹ̀, àti àwọn ènìyàn náà tí ó ti yàn ṣe ìní rẹ̀.
Błogosławiony naród, którego Pan jest Bogiem jego; lud, który sobie obrał za dziedzictwo.
13 Olúwa wò láti ọ̀run wá; Ó sì rí gbogbo ìran ènìyàn.
Pan patrzy z nieba, i widzi wszystkich synów ludzkich.
14 Níbi tí ó ti jókòó lórí ìtẹ́ Ó wo gbogbo àwọn olùgbé ayé
Z miejsca mieszkania swego spogląda na wszystkich obywateli ziemi.
15 ẹni tí ó ṣe àyà wọn bákan náà, ó sì kíyèsi ìṣe wọn.
Który stworzył serce każdego z nich, upatruje wszystkie sprawy ich.
16 A kò gba ọba kan là nípasẹ̀ ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ọmọ-ogun; kò sì sí jagunjagun tí a gbà sílẹ̀ nípa agbára ńlá rẹ̀.
Nie bywa król wybawiony przez wielkość wojska, ani mocarz nie ujdzie przez wielką moc swoję.
17 Ohun asán ni ẹṣin fún ìṣẹ́gun; bẹ́ẹ̀ ni kì yóò fi agbára ńlá rẹ̀ gbani sílẹ̀.
Omylnyć jest koń ku wybawieniu, a nie wyrywa wielkością mocy swojej.
18 Wò ó, ojú Olúwa wà lára àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀, àti lára àwọn tí ó ní ìrètí nínú ìfẹ́ rẹ̀ tí ó dúró ṣinṣin.
Oto oko Pańskie nad tymi, którzy się go boją, nad tymi, którzy ufają w miłosierdziu jego;
19 Láti gba ọkàn wọn kúrò lọ́wọ́ ikú àti láti pa wọ́n mọ́ láààyè lọ́wọ́ ìyàn.
Aby wyrwał od śmierci duszę ich, a pożywił ich w głodzie.
20 Ọkàn wa dúró de Olúwa; òun ni ìrànlọ́wọ́ wa àti asà wa.
Dusza nasza oczekuje Pana; on ratunek nasz i tarcza nasza.
21 Ọkàn wa yọ̀ nínú rẹ̀, nítorí pé, àwa gbẹ́kẹ̀lé orúkọ rẹ mímọ́.
W nim zaprawdę rozweseli się serce nasze; bo w imieniu jego świętem ufamy.
22 Kí àánú rẹ, Olúwa, kí ó wà lára wa, àní gẹ́gẹ́ bí àwa ti ń ṣe ìrètí nínú rẹ.
Niechże będzie miłosierdzie twoje, Panie! nad nami, jakośmy nadzieję w tobie mieli.

< Psalms 33 >