< Psalms 33 >

1 Ẹ yọ̀ nínú Olúwa, ẹ̀yin olódodo; ìyìn si yẹ fún ẹni dídúró ṣinṣin.
Justes, réjouissez-vous en l'Éternel! La louange convient aux hommes droits.
2 Ẹ yin Olúwa pẹ̀lú dùùrù; ẹ máa fi ohun èlò olókùn mẹ́wàá kọrin sí i.
Célébrez l'Éternel avec la harpe; chantez-lui des cantiques sur la lyre à dix cordes!
3 Ẹ kọ orin tuntun sí i; ẹ máa fi ọgbọọgbọ́n lu ohun èlò orin sí i, pẹ̀lú ariwo.
Chantez-lui un cantique nouveau; faites retentir vos instruments et vos voix!
4 Nítorí pé ọ̀rọ̀ Olúwa dúró ṣinṣin, gbogbo iṣẹ́ rẹ̀ ni à ń ṣe nínú òtítọ́.
Car la parole de l'Éternel est droite, et toute son œuvre est faite avec fidélité.
5 Ó fẹ́ òtítọ́ àti ìdájọ́; ilé ayé kún fún ìdúró ṣinṣin àti àánú Olúwa.
Il aime la justice et l'équité; la terre est pleine de la bonté de l'Éternel.
6 Nípasẹ̀ ọ̀rọ̀ Olúwa ni a ṣe dá àwọn ọ̀run, àti gbogbo àwọn ẹgbẹ́ ogun wọn nípa ìmísí ẹnu rẹ̀.
Les cieux ont été faits par la parole de l'Éternel, et toute leur armée par le souffle de sa bouche.
7 Ó kó àwọn omi òkun jọ gẹ́gẹ́ bí èyí tí ó wà nínú ìgò; ó sì fi ibú ṣe ilé ìṣúra gbogbo.
Il amasse les eaux de la mer comme en un monceau; il met les flots dans des réservoirs.
8 Jẹ́ kí gbogbo ayé kí ó bẹ̀rù Olúwa: jẹ́ kí gbogbo àwọn olùgbé ayé kí ó wà nínú ìbẹ̀rù rẹ̀.
Que toute la terre craigne l'Éternel; que tous les habitants du monde le redoutent!
9 Nítorí tí ó sọ̀rọ̀, ó sì ti rí bẹ́ẹ̀; ó pàṣẹ ó sì dúró ṣinṣin.
Car il parle, et la chose existe; il commande, et elle paraît.
10 Olúwa ti mú ìmọ̀ràn àwọn orílẹ̀-èdè wá sí asán; ó sì mú àrékérekè àwọn ènìyàn di ṣíṣákì í.
L'Éternel dissipe le conseil des nations, il met à néant le dessein des peuples.
11 Ìgbìmọ̀ Olúwa dúró títí ayérayé, àní ìrò inú rẹ̀ láti ìrandíran ni.
Mais le conseil de l'Éternel subsiste à toujours; les desseins de son cœur durent d'âge en âge.
12 Ìbùkún ni fún orílẹ̀-èdè náà, Ọlọ́run ẹni tí Olúwa jẹ́ tirẹ̀, àti àwọn ènìyàn náà tí ó ti yàn ṣe ìní rẹ̀.
Heureuse la nation dont l'Éternel est le Dieu, le peuple qu'il s'est choisi pour héritage!
13 Olúwa wò láti ọ̀run wá; Ó sì rí gbogbo ìran ènìyàn.
L'Éternel regarde des cieux; il voit tous les enfants des hommes.
14 Níbi tí ó ti jókòó lórí ìtẹ́ Ó wo gbogbo àwọn olùgbé ayé
Du lieu de sa demeure, il observe tous les habitants de la terre.
15 ẹni tí ó ṣe àyà wọn bákan náà, ó sì kíyèsi ìṣe wọn.
Il a formé leur cœur à tous, il prend garde à toutes leurs actions.
16 A kò gba ọba kan là nípasẹ̀ ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ọmọ-ogun; kò sì sí jagunjagun tí a gbà sílẹ̀ nípa agbára ńlá rẹ̀.
Le roi n'est pas sauvé par sa grande puissance, et l'homme vaillant n'est pas délivré par sa grande force.
17 Ohun asán ni ẹṣin fún ìṣẹ́gun; bẹ́ẹ̀ ni kì yóò fi agbára ńlá rẹ̀ gbani sílẹ̀.
Le cheval manque à sauver, et il ne délivre point par la grandeur de sa force.
18 Wò ó, ojú Olúwa wà lára àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀, àti lára àwọn tí ó ní ìrètí nínú ìfẹ́ rẹ̀ tí ó dúró ṣinṣin.
Voici, l'œil de l'Éternel est sur ceux qui le craignent, sur ceux qui s'attendent à sa bonté,
19 Láti gba ọkàn wọn kúrò lọ́wọ́ ikú àti láti pa wọ́n mọ́ láààyè lọ́wọ́ ìyàn.
Pour délivrer leur âme de la mort, et pour les faire vivre durant la famine.
20 Ọkàn wa dúró de Olúwa; òun ni ìrànlọ́wọ́ wa àti asà wa.
Notre âme s'attend à l'Éternel; il est notre aide et notre bouclier.
21 Ọkàn wa yọ̀ nínú rẹ̀, nítorí pé, àwa gbẹ́kẹ̀lé orúkọ rẹ mímọ́.
Car notre cœur se réjouit en lui; car nous nous confions en son saint nom.
22 Kí àánú rẹ, Olúwa, kí ó wà lára wa, àní gẹ́gẹ́ bí àwa ti ń ṣe ìrètí nínú rẹ.
Que ta bonté soit sur nous, ô Éternel! comme nous nous attendons à toi.

< Psalms 33 >