< Psalms 33 >

1 Ẹ yọ̀ nínú Olúwa, ẹ̀yin olódodo; ìyìn si yẹ fún ẹni dídúró ṣinṣin.
Justes, réjouissez-vous en Yahweh! Aux hommes droits sied la louange.
2 Ẹ yin Olúwa pẹ̀lú dùùrù; ẹ máa fi ohun èlò olókùn mẹ́wàá kọrin sí i.
Célébrez Yahweh avec la harpe, chantez-le sur le luth à dix cordes.
3 Ẹ kọ orin tuntun sí i; ẹ máa fi ọgbọọgbọ́n lu ohun èlò orin sí i, pẹ̀lú ariwo.
Chantez à sa gloire un cantique nouveau; unissez avec art vos instruments et vos voix.
4 Nítorí pé ọ̀rọ̀ Olúwa dúró ṣinṣin, gbogbo iṣẹ́ rẹ̀ ni à ń ṣe nínú òtítọ́.
Car la parole de Yahweh est droite, et toutes ses œuvres s’accomplissent dans la fidélité.
5 Ó fẹ́ òtítọ́ àti ìdájọ́; ilé ayé kún fún ìdúró ṣinṣin àti àánú Olúwa.
il aime la justice et la droiture; la terre est remplie de la bonté de Yahweh.
6 Nípasẹ̀ ọ̀rọ̀ Olúwa ni a ṣe dá àwọn ọ̀run, àti gbogbo àwọn ẹgbẹ́ ogun wọn nípa ìmísí ẹnu rẹ̀.
Par la parole de Yahweh les cieux ont été faits, et toute leur armée par le souffle de sa bouche.
7 Ó kó àwọn omi òkun jọ gẹ́gẹ́ bí èyí tí ó wà nínú ìgò; ó sì fi ibú ṣe ilé ìṣúra gbogbo.
Il rassemble comme en un monceau les eaux de la mer; il met dans des réservoirs les flots de l’abîme.
8 Jẹ́ kí gbogbo ayé kí ó bẹ̀rù Olúwa: jẹ́ kí gbogbo àwọn olùgbé ayé kí ó wà nínú ìbẹ̀rù rẹ̀.
Que toute la terre craigne Yahweh! Que tous les habitants de l’univers tremblent devant lui!
9 Nítorí tí ó sọ̀rọ̀, ó sì ti rí bẹ́ẹ̀; ó pàṣẹ ó sì dúró ṣinṣin.
Car il a dit, et tout a été fait; il a ordonné, et tout a existé.
10 Olúwa ti mú ìmọ̀ràn àwọn orílẹ̀-èdè wá sí asán; ó sì mú àrékérekè àwọn ènìyàn di ṣíṣákì í.
Yahweh renverse les desseins des nations; il réduit à néant les pensées des peuples.
11 Ìgbìmọ̀ Olúwa dúró títí ayérayé, àní ìrò inú rẹ̀ láti ìrandíran ni.
Mais les desseins de Yahweh subsistent à jamais et les pensées de son cœur dans toutes les générations.
12 Ìbùkún ni fún orílẹ̀-èdè náà, Ọlọ́run ẹni tí Olúwa jẹ́ tirẹ̀, àti àwọn ènìyàn náà tí ó ti yàn ṣe ìní rẹ̀.
Heureuse la nation dont Yahweh est le Dieu, heureux le peuple qu’il a choisi pour son héritage!
13 Olúwa wò láti ọ̀run wá; Ó sì rí gbogbo ìran ènìyàn.
Du haut des cieux Yahweh regarde, il voit tous les enfants des hommes;
14 Níbi tí ó ti jókòó lórí ìtẹ́ Ó wo gbogbo àwọn olùgbé ayé
du lieu de sa demeure, il observe tous les habitants de la terre,
15 ẹni tí ó ṣe àyà wọn bákan náà, ó sì kíyèsi ìṣe wọn.
lui qui forme leur cœur à tous, qui est attentif à toutes leurs actions.
16 A kò gba ọba kan là nípasẹ̀ ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ọmọ-ogun; kò sì sí jagunjagun tí a gbà sílẹ̀ nípa agbára ńlá rẹ̀.
Ce n’est pas le nombre des soldats qui donne au roi la victoire, ce n’est pas une grande force qui fait triompher le guerrier.
17 Ohun asán ni ẹṣin fún ìṣẹ́gun; bẹ́ẹ̀ ni kì yóò fi agbára ńlá rẹ̀ gbani sílẹ̀.
Le cheval est impuissant à procurer le salut, et toute sa vigueur n’assure pas la délivrance.
18 Wò ó, ojú Olúwa wà lára àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ̀, àti lára àwọn tí ó ní ìrètí nínú ìfẹ́ rẹ̀ tí ó dúró ṣinṣin.
L’œil de Yahweh est sur ceux qui le craignent, sur ceux qui espèrent en sa bonté,
19 Láti gba ọkàn wọn kúrò lọ́wọ́ ikú àti láti pa wọ́n mọ́ láààyè lọ́wọ́ ìyàn.
pour délivrer leur âme de la mort, et les faire vivre au temps de la famine.
20 Ọkàn wa dúró de Olúwa; òun ni ìrànlọ́wọ́ wa àti asà wa.
Notre âme attend avec confiance Yahweh; il est notre secours et notre bouclier;
21 Ọkàn wa yọ̀ nínú rẹ̀, nítorí pé, àwa gbẹ́kẹ̀lé orúkọ rẹ mímọ́.
car en lui notre cœur met sa joie, car en son saint nom nous mettons notre confiance.
22 Kí àánú rẹ, Olúwa, kí ó wà lára wa, àní gẹ́gẹ́ bí àwa ti ń ṣe ìrètí nínú rẹ.
Yahweh, que ta grâce soit sur nous, comme nous espérons en toi!

< Psalms 33 >