< Psalms 32 >

1 Ti Dafidi. Maskili. Ìbùkún ni fún àwọn tí a dárí ìrékọjá wọn jì, tí a sì bo ẹ̀ṣẹ̀ wọn mọ́lẹ̀.
Pieśń Dawidowa nauczająca. Błogosławiony człowiek, któremu odpuszczono nieprawość, a którego zakryty jest grzech.
2 Ìbùkún ni fún ọkùnrin náà ẹni tí Olúwa kò ka ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ sí i lọ́rùn àti nínú ẹ̀mí ẹni tí kò sí ẹ̀tàn.
Błogosławiony człowiek, któremu nie poczyta Pan nieprawości, a w którego duchu nie masz zdrady.
3 Nígbà tí mo dákẹ́, egungun mi di gbígbó dànù nípa ìkérora mi ní gbogbo ọjọ́.
Gdym milczał, schnęły kości moje w narzekaniu mojem na każdy dzień.
4 Nítorí pé ni ọ̀sán àti ní òru ọwọ́ rẹ̀ wúwo sí mi lára; agbára mi gbẹ tán gẹ́gẹ́ bí ooru ẹ̀ẹ̀rùn. (Sela)
Ponieważ we dnie i w nocy ociężała nademną ręka twoja, obróciła się wilgotność moja w suszę letnią. (Sela)
5 Èmi jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ mi sí ọ àti pé èmi kò sì fi àìṣòdodo mi pamọ́. Èmi wí pé, “Èmi yóò jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ mi fún Olúwa,” ìwọ sì dárí ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ mi jì mí. (Sela)
przetoż grzech mój oznajmiłem tobie, a nieprawości mojej nie kryłem. Rzekłem: Wyznam na się przestępstwa moje Panu, a tyś odpuścił nieprawość grzechu mego. (Sela)
6 Nítorí náà jẹ́ kí gbogbo àwọn olódodo máa gbà àdúrà sí ọ ní ìgbà tí a lè rí ọ; nítòótọ́ nígbà tí ìṣàn omi ńlá bá ru sókè, wọn kì yóò lè dé ọ̀dọ̀ rẹ̀.
Oto się tobie będzie modlił każdy święty, czasu, którego możesz być znaleziony, a choć wzbiorą powodzi wód wielkich, przecież go nie dosięgną.
7 Ìwọ ni ibi ìpamọ́ mi; ìwọ yóò pa mí mọ́ kúrò nínú ìyọnu; ìwọ yóò fi orin ìgbàlà yí mi ka. (Sela)
Tyś jest ucieczką moją; od uciśnienia zachowasz mię, i piosnkami radosnego wybawienia uraczysz mię. (Sela)
8 Èmi yóò kọ́ ọ, èmi yóò sì fi ẹsẹ̀ rẹ lé ọ̀nà tí ìwọ yóò rìn èmi yóò máa gbà ọ́ ní ìyànjú, èmi yóò sì máa fi ojú mi tọ́ ọ.
Dam ci rozum, i nauczę cię drogi, po której masz chodzić; dam ci radę, obróciwszy na cię oko moje.
9 Má ṣe dàbí ẹṣin tàbí ìbáaka, tí kò ní òye ẹnu ẹni tí a gbọdọ̀ fi ìjánu bọ̀, kí wọn má ba à súnmọ́ ọ.
Nie bądźcież jako koń, albo jako muł, którzy rozumu nie mają, których gęby uzdą i wędzidłem kiełznać musisz, aby się na cię nie porywały.
10 Ọ̀pọ̀ ìkáàánú ní yóò wà fún ènìyàn búburú, ṣùgbọ́n ìfẹ́ Olúwa tí ó dúró ṣinṣin ni yóò yí àwọn tí ó ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú Olúwa ká.
Wiele boleści przypada na złośnika; ale ufającego w Panu miłosierdzie ogarnie.
11 Ẹ yọ̀ nínú Olúwa, kí ẹ sì ní inú dídùn, ẹ̀yìn olódodo; ẹ sì máa kọrin, gbogbo ẹ̀yìn tí àyà yín dúró ṣinṣin.
Weselcie się w Panu, i radujcie się sprawiedliwi, a wykrzykajcie wszyscy, którzyście serca szczerego.

< Psalms 32 >