< Psalms 31 >

1 Fún adarí orin. Saamu ti Dafidi. Nínú rẹ̀, Olúwa ni mo ti rí ààbò; má ṣe jẹ́ kí ojú kí ó tì mí; gbà mí nínú òdodo rẹ.
Dāvida dziesma. Dziedātāju vadonim. Uz tevi, Kungs, es paļaujos, nepamet mani kaunā mūžīgi, izglāb mani caur Tavu taisnību.
2 Tẹ́ etí rẹ sí mi, gbà mí kíákíá; jẹ́ àpáta ààbò mi, jẹ́ odi alágbára láti gbà mí.
Atgriez Savu ausi pie manis, izglāb mani drīz, esi man par stipru patvērumu, par stipru pili man palīdzēt.
3 Ìwọ pàápàá ni àpáta àti ààbò mi, nítorí orúkọ rẹ, máa ṣe olùtọ́ mi, kí o sì ṣe amọ̀nà mi.
Jo Tu esi mans akmens kalns un mana stiprā pils, un Tava Vārda dēļ ved un vadi mani.
4 Yọ mí jáde kúrò nínú àwọ̀n tí wọ́n dẹ pamọ́ fún mi, nítorí ìwọ ni ìsádi mi.
Izved mani no tīkla, ko tie priekš manis paslēpuši, jo Tu esi mans stiprums.
5 Ní ọwọ́ rẹ ni mo fi ẹ̀mí mi lé; ìwọ ni o ti rà mí padà, Olúwa, Ọlọ́run òtítọ́.
Tavā rokā es pavēlu savu garu, Tu mani esi atpestījis, Kungs, Tu stiprais patiesības Dievs.
6 Èmi ti kórìíra àwọn ẹni tí ń fiyèsí òrìṣà tí kò níye lórí; ṣùgbọ́n èmi gbẹ́kẹ̀lé Olúwa.
Es ienīstu tos, kas dodas uz blēņu mācībām, bet es paļaujos uz To Kungu.
7 Èmi yóò yọ̀, inú mi yóò dùn nínú ìfẹ́ ńlá rẹ, nítorí ìwọ ti rí ìbìnújẹ́ mi ìwọ ti mọ̀ ọkàn mi nínú ìpọ́njú.
Es priecāšos un līksmošos par Tavu žēlastību, ka Tu uzlūko manas bēdas, un vērā lieci manu dvēseli bailēs,
8 Pẹ̀lú, ìwọ kò sì fà mi lé àwọn ọ̀tá lọ́wọ́ ìwọ ti fi ẹsẹ̀ mi lé ibi ààyè ńlá.
Un nenodod mani ienaidnieka rokā; Tu manām kājām lieci stāvēt plašā vietā.
9 Ṣàánú fún mi, ìwọ Olúwa, nítorí mo wà nínú ìpọ́njú; ojú mi fi ìbìnújẹ́ sùn, ọkàn àti ara mi pẹ̀lú.
Esi man žēlīgs, ak Kungs! Jo man ir bail', no skumības ir sarucis mans vaigs, mana dvēsele un mana miesa.
10 Èmi fi ìbànújẹ́ lo ọjọ́ mi àti àwọn ọdún mi pẹ̀lú ìmí ẹ̀dùn; agbára mi ti kùnà nítorí òsì mi, egungun mi sì ti rún dànù.
Jo mana dzīvība ir nonīkusi caur noskumšanu un mani gadi caur nopūšanos, mans spēks caur manu noziegumu ir sakritis, un mani kauli ir sanīkuši.
11 Èmi di ẹni ẹ̀gàn láàrín àwọn ọ̀tá mi gbogbo, pẹ̀lúpẹ̀lú láàrín àwọn aládùúgbò mi, mo sì di ẹ̀rù fún àwọn ojúlùmọ̀ mi; àwọn tí ó rí mi ní òde ń yẹra fún mi.
Caur visiem saviem pretiniekiem es esmu par kaunu tapis saviem kaimiņiem, un saviem pazīstamiem par biedēkli; kas mani uz ielām redz, tie bēg no manis.
12 Èmi ti di ẹni ìgbàgbé kúrò ní ọkàn gẹ́gẹ́ bí ẹni tí ó ti kú; èmi sì dàbí ohun èlò tí ó ti fọ́.
Es sirdīs esmu aizmirsts kā mironis, esmu tapis kā sadauzīts trauks.
13 Nítorí mo gbọ́ ọ̀rọ̀ ẹ̀gàn ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìpayà tí ó yí mi ká; tí wọn gbìmọ̀ pọ̀ sí mi, wọ́n sì ṣọ̀tẹ̀ sí mi láti gba ẹ̀mí mi.
Jo es dzirdu no daudziem lamāšanās: bailība ir visapkārt; kad tie kopā sarunājās pret mani, tie domā paņemt manu dzīvību.
14 Ṣùgbọ́n èmí gbẹ́kẹ̀lé ọ, ìwọ Olúwa; mo sọ wí pé, “Ìwọ ní Ọlọ́run mi.”
Bet es cerēju uz Tevi, Kungs; es saku tā: Tu esi mans Dievs.
15 Ìgbà mi ń bẹ ní ọwọ́ rẹ; gbà mí kúrò ní ọwọ́ àwọn ọ̀tá mi àti àwọn onínúnibíni.
Mani laiki stāv Tavā rokā; izglāb mani no manu ienaidnieku rokas un no tiem, kas mani vajā.
16 Jẹ́ kí ojú rẹ kí ó tan ìmọ́lẹ̀ sí ìránṣẹ́ rẹ lára; gbà mí nínú ìfẹ́ rẹ tí ó dúró ṣinṣin.
Liec Savam vaigam spīdēt pār Savu kalpu, atpestī mani caur Tavu žēlastību.
17 Má ṣe jẹ́ kí ojú ki ó tì mí, Olúwa; nítorí pé mo ké pè ọ́; jẹ́ kí ojú kí ó ti ènìyàn búburú; jẹ́ kí wọ́n lọ pẹ̀lú ìdààmú sí isà òkú. (Sheol h7585)
Kungs, neliec man kaunā palikt, jo es Tevi piesaucu; lai bezdievīgie paliek kaunā un top klusināti ellē. (Sheol h7585)
18 Jẹ́ kí àwọn ètè irọ́ kí ó dákẹ́ jẹ́ẹ́, pẹ̀lú ìgbéraga àti ìkẹ́gàn, wọ́n sọ̀rọ̀ àfojúdi sí olódodo.
Lai mēmas paliek melkuļu lūpas kas bezkaunīgi runā pret taisno ar lepnību un nicināšanu.
19 Báwo ni títóbi oore rẹ̀ ti pọ̀ tó, èyí tí ìwọ ti ní ní ìpamọ́ fún àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ, èyí tí ìwọ rọ̀jò rẹ̀ níwájú àwọn ènìyàn tí wọ́n fi ọ́ ṣe ibi ìsádi wọn.
Cik liels ir Tavs labums, ko Tu esi glabājis tiem, kas Tevi bīstas, un sataisījis tiem, kas cilvēku priekšā uz Tevi paļaujas.
20 Ní abẹ́ ìbòòji iwájú rẹ ni ìwọ pa wọ́n mọ́ sí kúrò nínú ìdìmọ̀lù àwọn ènìyàn; ní ibùgbé rẹ, o mú wọn kúrò nínú ewu kúrò nínú ìjà ahọ́n.
Tu tos slēpi Sava vaiga ēnā priekš cilvēku dumpjiem, Tu tos glabā kā namā priekš rējēju mēlēm.
21 Olùbùkún ni Olúwa, nítorí pé ó ti fi àgbà ìyanu ìfẹ́ tí ó ní sí mi hàn, nígbà tí mo wà ní ìlú tí wọ́n rọ̀gbà yíká.
Slavēts lai ir Tas Kungs, jo Viņš brīnišķi man parādījis Savu žēlastību tā kā stiprā pilsētā.
22 Èmí ti sọ nínú ìdágìrì mi, “A gé mi kúrò ní ojú rẹ!” Síbẹ̀ ìwọ ti gbọ́ ẹ̀bẹ̀ mi fún àánú nígbà tí mo ké pè ọ́ fún ìrànlọ́wọ́.
Gan es sacīju savās bailēs: es esmu atmests no Tava vaiga; taču Tu klausīji manas sirds lūgšanas balsi, kad es Tevi piesaucu.
23 Ẹ fẹ́ Olúwa, gbogbo ẹ̀yin ènìyàn rẹ̀ mímọ́! Olúwa pa olódodo mọ́, ó sì san án padà fún agbéraga ní ẹ̀kúnrẹ́rẹ́.
Mīlējiet To Kungu, visi Viņa svētie; Tas Kungs pasargā tos ticīgos, un atmaksā papilnam tam, kas dara pārgalvību.
24 Jẹ́ alágbára, yóò sì mú yín ní àyà le gbogbo ẹ̀yin tí ó dúró de Olúwa.
Esiet droši un stipri savā sirdī, visi, kas cerējiet uz To Kungu.

< Psalms 31 >