< Psalms 30 >

1 Saamu. Orin. Fún ìyàsímímọ́ Tẹmpili. Ti Dafidi. Èmi yóò kókìkí i rẹ, Olúwa, nítorí ìwọ ni ó gbé mi lékè tí ìwọ kò sì jẹ́ kí àwọn ọ̀tá mi kí ó yọ̀ mí.
Psalm i pieśń na poświęcenie przybytku Dawida. PANIE, będę cię wywyższać, bo podniosłeś mnie i nie pozwoliłeś mym wrogom cieszyć się z mojego powodu.
2 Olúwa Ọlọ́run mi, èmi ké pè ọ́ fún ìrànlọ́wọ́, ìwọ sì ti wò mí sàn.
PANIE, Boże mój, wołałem do ciebie i uzdrowiłeś mnie.
3 Olúwa, ìwọ ti yọ ọkàn mi jáde kúrò nínú isà òkú, mú mi padà bọ̀ sípò alààyè kí èmi má ba à lọ sínú ihò. (Sheol h7585)
PANIE, wyprowadziłeś moją duszę z piekła, zachowałeś mnie przy życiu, abym nie zstąpił do dołu. (Sheol h7585)
4 Kọ orin ìyìn sí Olúwa, ẹ̀yin olódodo; kí ẹ sì fi ọpẹ́ fún orúkọ rẹ̀ mímọ́.
Śpiewajcie PANU, święci jego, i wysławiajcie [go], wspominając jego świętość.
5 Nítorí pé ìbínú rẹ̀ wà fún ìgbà díẹ̀, ojúrere rẹ̀ wà títí ayérayé; ẹkún lè pẹ́ títí di alẹ́, ṣùgbọ́n ayọ̀ yóò wá ní òwúrọ̀.
Jego gniew bowiem trwa tylko chwilę, a jego łaskawość przez [całe] życie; choćby płacz trwał przez noc, rankiem nastanie radość.
6 Ní ìgbà ayé mi, mo wí pé, “a kì yóò ṣí mi ní ipò padà.”
Powiedziałem w czasie mej pomyślności: Nigdy się nie zachwieję.
7 Nípa ojúrere rẹ, Olúwa, ìwọ ti gbé mi kalẹ̀ bí òkè tí ó ní agbára; ìwọ pa ojú rẹ mọ́, àyà sì fò mí.
PANIE, w swojej łaskawości umocniłeś moją górę; ale gdy ukryłeś swoje oblicze, strwożyłem się.
8 Sí ọ Olúwa, ni mo ké pè é; àti sí Olúwa ni mo sọkún fún àánú:
Wołałem do ciebie, PANIE, modliłem się do PANA:
9 “Èrè kí ni ó wà nínú ikú ìparun mi, nínú lílọ sí ihò mi? Eruku yóò a yìn ọ́ bí? Ǹjẹ́ yóò sọ nípa òdodo rẹ?
Jaki pożytek z mojej krwi, gdybym zstąpił do dołu? Czy proch będzie cię chwalić? Czy będzie głosić twoją prawdę?
10 Gbọ́, Olúwa, kí o sì ṣàánú fún mi; ìwọ Olúwa, jẹ́ olùrànlọ́wọ́ mi.”
Usłysz, PANIE, i zmiłuj się nade mną; PANIE, bądź moim pomocnikiem.
11 Ìwọ ti yí ìkáàánú mi di ijó fún mi; ìwọ sì ti bọ́ aṣọ ọ̀fọ̀ mi, o sì fi aṣọ ayọ̀ wọ̀ mí,
Mój płacz zmieniłeś w taniec, zdjąłeś [ze mnie] wór [pokutny], a przepasałeś mnie radością;
12 nítorí ìdí èyí ni kí ọkàn mi máa yìn ọ́, kí o má sì ṣe dákẹ́. Ìwọ Olúwa Ọlọ́run mi, èmi yóò máa fi ọpẹ́ fún ọ títí láé.
Aby [moja] chwała śpiewała ci i nie milkła; PANIE, mój Boże, będę cię wysławiać na wieki.

< Psalms 30 >