< Psalms 3 >
1 Saamu ti Dafidi. Nígbà ti ó sá fún ọmọ rẹ̀ Absalomu. Olúwa, báwo ni àwọn ọ̀tá mi ṣe pọ̀ tó báyìí! Báwo ni àwọn ti ó dìde sí mi ṣe pọ̀ tó!
Un psaume de David, lorsqu'il fuyait Absalom, son fils. Yahvé, comme mes adversaires se sont multipliés! Nombreux sont ceux qui s'élèvent contre moi.
2 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni ó ń sọ ní ti tèmi, pé “Ọlọ́run kò nígbà á là.” (Sela)
Nombreux sont ceux qui disent de mon âme, « Il n'y a aucun secours pour lui en Dieu. (Selah)
3 Ṣùgbọ́n ìwọ ni asà yí mi ká, Olúwa; ìwọ fi ògo fún mi, ìwọ sì gbé orí mi sókè.
Mais toi, Yahvé, tu es un bouclier autour de moi, ma gloire, et celui qui relève ma tête.
4 Olúwa ni mo kígbe sókè sí, ó sì dá mi lóhùn láti orí òkè mímọ́ rẹ̀ wá. (Sela)
Je crie à Yahvé de ma voix, et il me répond du haut de sa colline sainte. (Selah)
5 Èmi dùbúlẹ̀, mo sì sùn; mo sì tún padà jí, nítorí Olúwa ni ó ń gbé mi ró.
Je me suis couché et j'ai dormi. Je me suis réveillé, car Yahvé me soutient.
6 Èmi kì yóò bẹ̀rù ẹgbẹẹgbẹ̀rún ènìyàn tí wọ́n rọ̀gbà yí mi ká.
Je n'aurai pas peur de dizaines de milliers de personnes. qui se sont dressés contre moi de toutes parts.
7 Dìde, Olúwa! Gbà mí, Ọlọ́run mi! Lu gbogbo àwọn ọ̀tá mi ní àgbọ̀n; kí o sì ká eyín àwọn ènìyàn búburú.
Lève-toi, Yahvé! Sauve-moi, mon Dieu! Car tu as frappé tous mes ennemis sur la pommette. Tu as cassé les dents des méchants.
8 Láti ọ̀dọ̀ Olúwa ni ìgbàlà ti wá. Kí ìbùkún rẹ wà lórí àwọn ènìyàn rẹ. (Sela)
Le salut appartient à Yahvé. Que ta bénédiction soit sur ton peuple. (Selah)