< Psalms 3 >

1 Saamu ti Dafidi. Nígbà ti ó sá fún ọmọ rẹ̀ Absalomu. Olúwa, báwo ni àwọn ọ̀tá mi ṣe pọ̀ tó báyìí! Báwo ni àwọn ti ó dìde sí mi ṣe pọ̀ tó!
`The salm of Dauid, whanne he fledde fro the face of Absolon, his sone. Lord, whi ben thei multiplied that disturblen me?
2 Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni ó ń sọ ní ti tèmi, pé “Ọlọ́run kò nígbà á là.” (Sela)
many men rysen ayens me. Many men seien of my soule, Noon helthe is to hym in his God.
3 Ṣùgbọ́n ìwọ ni asà yí mi ká, Olúwa; ìwọ fi ògo fún mi, ìwọ sì gbé orí mi sókè.
But thou, Lord, art myn vptakere; my glorye, and enhaunsyng myn heed.
4 Olúwa ni mo kígbe sókè sí, ó sì dá mi lóhùn láti orí òkè mímọ́ rẹ̀ wá. (Sela)
With my vois Y criede to the Lord; and he herde me fro his hooli hil.
5 Èmi dùbúlẹ̀, mo sì sùn; mo sì tún padà jí, nítorí Olúwa ni ó ń gbé mi ró.
I slepte, and `was quenchid, and Y roos vp; for the Lord resseyuede me.
6 Èmi kì yóò bẹ̀rù ẹgbẹẹgbẹ̀rún ènìyàn tí wọ́n rọ̀gbà yí mi ká.
I schal not drede thousyndis of puple cumpassynge me; Lord, rise thou vp; my God, make thou me saaf.
7 Dìde, Olúwa! Gbà mí, Ọlọ́run mi! Lu gbogbo àwọn ọ̀tá mi ní àgbọ̀n; kí o sì ká eyín àwọn ènìyàn búburú.
For thou hast smyte alle men beynge aduersaries to me with out cause; thou hast al to-broke the teeth of synneris.
8 Láti ọ̀dọ̀ Olúwa ni ìgbàlà ti wá. Kí ìbùkún rẹ wà lórí àwọn ènìyàn rẹ. (Sela)
Helthe is of the Lord; and thi blessyng, Lord, is on thi puple.

< Psalms 3 >