< Psalms 29 >

1 Saamu ti Dafidi. Ẹ fi fún Olúwa, ẹ̀yin ẹ̀dá ọ̀run, ẹ fi fún Olúwa, ògo àti alágbára.
¡Tributen a Yavé, oh hijos de los poderosos! ¡Tributen a Yavé la gloria y el poder!
2 Fi fún Olúwa, àní ògo orúkọ rẹ̀; sin Olúwa nínú ẹwà ìwà mímọ́.
¡Tributen a Yavé la gloria debida a su Nombre! ¡Póstrense ante Yavé en el esplendor de la santidad!
3 Ohùn Olúwa n ré àwọn omi kọjá; Ọlọ́run ògo sán àrá, Olúwa san ara.
Voz de Yavé sobre las aguas: ¡El ʼElohim de gloria truena! ¡Yavé está sobre muchas aguas!
4 Ohùn Olúwa ní agbára; ohùn Olúwa kún fún ọláńlá.
Voz de Yavé es poderosa, Voz de Yavé es majestuosa.
5 Ohùn Olúwa fa igi kedari; Olúwa náà ló fọ́ igi kedari Lebanoni ya.
Voz de Yavé que quiebra los cedros, Yavé destroza los cedros del Líbano.
6 Ó mú Lebanoni fo bí i ọmọ màlúù, àti Sirioni bí ọmọ àgbáǹréré.
Él hace saltar al Líbano como un becerro.
7 Ohùn Olúwa ń ya bí ọwọ́ iná mọ̀nà.
Voz de Yavé que enciende llamaradas.
8 Ohùn Olúwa ń mi aginjù. Olúwa mi aginjù Kadeṣi.
Voz de Yavé que estremece el desierto. Yavé sacude al desierto de Cades.
9 Ohùn Olúwa ní ó lọ igi óákù, ó n mú abo àgbọ̀nrín bí, ó sì bọ́ igi igbó sí ìhòhò. Àti nínú tẹmpili rẹ̀ gbogbo ohùn wí pé, “Ògo!”
Voz de Yavé que estremece los robles y desnuda los bosques. En su Templo todos proclaman su gloria.
10 Olúwa jókòó, Ó sì jẹ ọba lórí ìṣàn omi; Olúwa jókòó lórí ìtẹ́ gẹ́gẹ́ bí Ọba títí láéláé.
Yavé preside en el diluvio. Yavé se sienta como Rey para siempre.
11 Kí Olúwa fi agbára fún àwọn ènìyàn rẹ̀; bùkún àwọn ènìyàn rẹ̀ pẹ̀lú àlàáfíà.
Yavé dará fortaleza a su pueblo. Yavé bendecirá a su pueblo con paz.

< Psalms 29 >