< Psalms 29 >
1 Saamu ti Dafidi. Ẹ fi fún Olúwa, ẹ̀yin ẹ̀dá ọ̀run, ẹ fi fún Olúwa, ògo àti alágbára.
Ein salme av David. Gjev Herren, de Guds søner, gjev Herren æra og magt!
2 Fi fún Olúwa, àní ògo orúkọ rẹ̀; sin Olúwa nínú ẹwà ìwà mímọ́.
Gjev Herren hans namns æra, tilbed Herren i heilag prydnad!
3 Ohùn Olúwa n ré àwọn omi kọjá; Ọlọ́run ògo sán àrá, Olúwa san ara.
Herrens røyst ljodar yver vatni, Gud den herlege torar, Herren yver dei store vatn.
4 Ohùn Olúwa ní agbára; ohùn Olúwa kún fún ọláńlá.
Herrens røyst ljodar med velde, Herrens røyst med herlegdom.
5 Ohùn Olúwa fa igi kedari; Olúwa náà ló fọ́ igi kedari Lebanoni ya.
Herrens røyst bryt sund cedertre, ja, Herren bryt sund cedertrei på Libanon.
6 Ó mú Lebanoni fo bí i ọmọ màlúù, àti Sirioni bí ọmọ àgbáǹréré.
Og han fær deim til å hoppa som ein kalv, Libanon og Sirjon som ein ung villukse.
7 Ohùn Olúwa ń ya bí ọwọ́ iná mọ̀nà.
Herrens røyst sprengjer eldslogar fram.
8 Ohùn Olúwa ń mi aginjù. Olúwa mi aginjù Kadeṣi.
Herrens røyst fær øydemarki til å skjelva, Herren fær øydemarki ved Kades til å skjelva.
9 Ohùn Olúwa ní ó lọ igi óákù, ó n mú abo àgbọ̀nrín bí, ó sì bọ́ igi igbó sí ìhòhò. Àti nínú tẹmpili rẹ̀ gbogbo ohùn wí pé, “Ògo!”
Herrens røyst fær hindarne til å kalva og snøyder skogarne, og i hans tempel segjer alt: «Æra!»
10 Olúwa jókòó, Ó sì jẹ ọba lórí ìṣàn omi; Olúwa jókòó lórí ìtẹ́ gẹ́gẹ́ bí Ọba títí láéláé.
Herren sat yver storflodi, og Herren sit konge til æveleg tid.
11 Kí Olúwa fi agbára fún àwọn ènìyàn rẹ̀; bùkún àwọn ènìyàn rẹ̀ pẹ̀lú àlàáfíà.
Herren gjeve sitt folk styrke, Herren velsigne sitt folk med fred!