< Psalms 29 >
1 Saamu ti Dafidi. Ẹ fi fún Olúwa, ẹ̀yin ẹ̀dá ọ̀run, ẹ fi fún Olúwa, ògo àti alágbára.
Psaume de David. Rendez à l'Éternel, vous, fils de Dieu, rendez à l'Éternel la gloire et la force!
2 Fi fún Olúwa, àní ògo orúkọ rẹ̀; sin Olúwa nínú ẹwà ìwà mímọ́.
Rendez à l'Éternel l'honneur dû à son nom; prosternez-vous devant l'Éternel dans une sainte magnificence!
3 Ohùn Olúwa n ré àwọn omi kọjá; Ọlọ́run ògo sán àrá, Olúwa san ara.
La voix de l'Éternel retentit sur les eaux; le Dieu de gloire, l'Éternel, fait tonner sur les grandes eaux.
4 Ohùn Olúwa ní agbára; ohùn Olúwa kún fún ọláńlá.
La voix de l'Éternel est puissante; la voix de l'Éternel est magnifique.
5 Ohùn Olúwa fa igi kedari; Olúwa náà ló fọ́ igi kedari Lebanoni ya.
La voix de l'Éternel brise les cèdres; l'Éternel brise les cèdres du Liban.
6 Ó mú Lebanoni fo bí i ọmọ màlúù, àti Sirioni bí ọmọ àgbáǹréré.
Il les fait bondir comme un veau; le Liban et le Sirion comme un jeune buffle.
7 Ohùn Olúwa ń ya bí ọwọ́ iná mọ̀nà.
La voix de l'Éternel jette des éclats de flammes de feu.
8 Ohùn Olúwa ń mi aginjù. Olúwa mi aginjù Kadeṣi.
La voix de l'Éternel fait trembler le désert; l'Éternel fait trembler le désert de Kadès.
9 Ohùn Olúwa ní ó lọ igi óákù, ó n mú abo àgbọ̀nrín bí, ó sì bọ́ igi igbó sí ìhòhò. Àti nínú tẹmpili rẹ̀ gbogbo ohùn wí pé, “Ògo!”
La voix de l'Éternel fait enfanter les biches; elle dépouille les forêts; et dans son temple chacun s'écrie: Gloire!
10 Olúwa jókòó, Ó sì jẹ ọba lórí ìṣàn omi; Olúwa jókòó lórí ìtẹ́ gẹ́gẹ́ bí Ọba títí láéláé.
L'Éternel régnait au déluge; l'Éternel siégera en roi éternellement.
11 Kí Olúwa fi agbára fún àwọn ènìyàn rẹ̀; bùkún àwọn ènìyàn rẹ̀ pẹ̀lú àlàáfíà.
L'Éternel donnera force à son peuple; l'Éternel bénira son peuple par la paix.