< Psalms 29 >

1 Saamu ti Dafidi. Ẹ fi fún Olúwa, ẹ̀yin ẹ̀dá ọ̀run, ẹ fi fún Olúwa, ògo àti alágbára.
Psaume de David. Célébrez l’Eternel, ô fils de Dieu! Célébrez sa gloire et sa puissance.
2 Fi fún Olúwa, àní ògo orúkọ rẹ̀; sin Olúwa nínú ẹwà ìwà mímọ́.
Rendez hommage au nom glorieux de l’Eternel, adorez l’Eternel dans son superbe sanctuaire.
3 Ohùn Olúwa n ré àwọn omi kọjá; Ọlọ́run ògo sán àrá, Olúwa san ara.
La voix de l’Eternel retentit sur les eaux, le Dieu de gloire tonne, l’Eternel, sur les grandes eaux.
4 Ohùn Olúwa ní agbára; ohùn Olúwa kún fún ọláńlá.
La voix de l’Eternel éclate avec force, la voix de l’Eternel, avec majesté.
5 Ohùn Olúwa fa igi kedari; Olúwa náà ló fọ́ igi kedari Lebanoni ya.
La voix de l’Eternel brise les cèdres, c’est l’Eternel qui met en pièces les cèdres du Liban,
6 Ó mú Lebanoni fo bí i ọmọ màlúù, àti Sirioni bí ọmọ àgbáǹréré.
qui les fait bondir comme de jeunes taureaux, le Liban et le Sirion comme de jeunes buffles.
7 Ohùn Olúwa ń ya bí ọwọ́ iná mọ̀nà.
La voix de l’Eternel fait jaillir des flammes ardentes;
8 Ohùn Olúwa ń mi aginjù. Olúwa mi aginjù Kadeṣi.
la voix de l’Eternel fait trembler le désert, l’Eternel fait trembler le désert de Kadêch.
9 Ohùn Olúwa ní ó lọ igi óákù, ó n mú abo àgbọ̀nrín bí, ó sì bọ́ igi igbó sí ìhòhò. Àti nínú tẹmpili rẹ̀ gbogbo ohùn wí pé, “Ògo!”
La voix de l’Eternel fait enfanter les biches, elle dépouille les forêts; dans son palais tous de s’écrier: "Gloire!"
10 Olúwa jókòó, Ó sì jẹ ọba lórí ìṣàn omi; Olúwa jókòó lórí ìtẹ́ gẹ́gẹ́ bí Ọba títí láéláé.
L’Eternel trônait lors du déluge; ainsi l’Eternel trône en roi pour l’éternité.
11 Kí Olúwa fi agbára fún àwọn ènìyàn rẹ̀; bùkún àwọn ènìyàn rẹ̀ pẹ̀lú àlàáfíà.
Que l’Eternel donne la force à son peuple! Que l’Eternel bénisse son peuple par la paix!

< Psalms 29 >