< Psalms 29 >
1 Saamu ti Dafidi. Ẹ fi fún Olúwa, ẹ̀yin ẹ̀dá ọ̀run, ẹ fi fún Olúwa, ògo àti alágbára.
Un psaume de David. Rendez hommage à Yahvé, fils de puissants, attribuer à Yahvé la gloire et la force.
2 Fi fún Olúwa, àní ògo orúkọ rẹ̀; sin Olúwa nínú ẹwà ìwà mímọ́.
Rendez à Yahvé la gloire due à son nom. Adorez Yahvé dans une tenue sacrée.
3 Ohùn Olúwa n ré àwọn omi kọjá; Ọlọ́run ògo sán àrá, Olúwa san ara.
La voix de Yahvé est sur les eaux. Le Dieu de gloire tonne, Yahvé sur les grandes eaux.
4 Ohùn Olúwa ní agbára; ohùn Olúwa kún fún ọláńlá.
La voix de Yahvé est puissante. La voix de Yahvé est pleine de majesté.
5 Ohùn Olúwa fa igi kedari; Olúwa náà ló fọ́ igi kedari Lebanoni ya.
La voix de Yahvé brise les cèdres. Oui, Yahvé brise en morceaux les cèdres du Liban.
6 Ó mú Lebanoni fo bí i ọmọ màlúù, àti Sirioni bí ọmọ àgbáǹréré.
Il les fait aussi sauter comme un veau; le Liban et le Sirion comme un jeune bœuf sauvage.
7 Ohùn Olúwa ń ya bí ọwọ́ iná mọ̀nà.
La voix de Yahvé frappe avec des éclairs.
8 Ohùn Olúwa ń mi aginjù. Olúwa mi aginjù Kadeṣi.
La voix de Yahvé fait trembler le désert. Yahvé secoue le désert de Kadesh.
9 Ohùn Olúwa ní ó lọ igi óákù, ó n mú abo àgbọ̀nrín bí, ó sì bọ́ igi igbó sí ìhòhò. Àti nínú tẹmpili rẹ̀ gbogbo ohùn wí pé, “Ògo!”
La voix de Yahvé fait vêler les biches, et dépouille les forêts. Dans son temple, tout dit: « Gloire! »
10 Olúwa jókòó, Ó sì jẹ ọba lórí ìṣàn omi; Olúwa jókòó lórí ìtẹ́ gẹ́gẹ́ bí Ọba títí láéláé.
Yahvé était assis sur un trône au moment du déluge. Oui, Yahvé siège comme roi pour toujours.
11 Kí Olúwa fi agbára fún àwọn ènìyàn rẹ̀; bùkún àwọn ènìyàn rẹ̀ pẹ̀lú àlàáfíà.
Yahvé donnera de la force à son peuple. Yahvé bénira son peuple par la paix.