< Psalms 29 >

1 Saamu ti Dafidi. Ẹ fi fún Olúwa, ẹ̀yin ẹ̀dá ọ̀run, ẹ fi fún Olúwa, ògo àti alágbára.
A psalm of David ascribe to Yahweh O sons of gods ascribe to Yahweh glory and strength.
2 Fi fún Olúwa, àní ògo orúkọ rẹ̀; sin Olúwa nínú ẹwà ìwà mímọ́.
Ascribe to Yahweh [the] glory of name his bow down to Yahweh in adornment of holiness.
3 Ohùn Olúwa n ré àwọn omi kọjá; Ọlọ́run ògo sán àrá, Olúwa san ara.
[the] voice of Yahweh [is] over the waters [the] God of glory he thunders Yahweh [is] over waters many.
4 Ohùn Olúwa ní agbára; ohùn Olúwa kún fún ọláńlá.
[the] voice of Yahweh [is] with strength [the] voice of Yahweh [is] with majesty.
5 Ohùn Olúwa fa igi kedari; Olúwa náà ló fọ́ igi kedari Lebanoni ya.
[the] voice of Yahweh [is] breaking cedars and he broke in pieces Yahweh [the] cedars of Lebanon.
6 Ó mú Lebanoni fo bí i ọmọ màlúù, àti Sirioni bí ọmọ àgbáǹréré.
And he made skip them like a calf Lebanon and Sirion like a young one of wild oxen.
7 Ohùn Olúwa ń ya bí ọwọ́ iná mọ̀nà.
[the] voice of Yahweh [is] striking flames of fire.
8 Ohùn Olúwa ń mi aginjù. Olúwa mi aginjù Kadeṣi.
[the] voice of Yahweh it causes to tremble [the] wilderness he causes to tremble Yahweh [the] wilderness of Kadesh.
9 Ohùn Olúwa ní ó lọ igi óákù, ó n mú abo àgbọ̀nrín bí, ó sì bọ́ igi igbó sí ìhòhò. Àti nínú tẹmpili rẹ̀ gbogbo ohùn wí pé, “Ògo!”
[the] voice of Yahweh - it causes labor pains to does and it stripped bare forests and in temple his all of it [is] saying glory.
10 Olúwa jókòó, Ó sì jẹ ọba lórí ìṣàn omi; Olúwa jókòó lórí ìtẹ́ gẹ́gẹ́ bí Ọba títí láéláé.
Yahweh to the flood he sat and he sat Yahweh king for ever.
11 Kí Olúwa fi agbára fún àwọn ènìyàn rẹ̀; bùkún àwọn ènìyàn rẹ̀ pẹ̀lú àlàáfíà.
Yahweh strength to people his he will give Yahweh - he will bless people his with peace.

< Psalms 29 >