< Psalms 29 >

1 Saamu ti Dafidi. Ẹ fi fún Olúwa, ẹ̀yin ẹ̀dá ọ̀run, ẹ fi fún Olúwa, ògo àti alágbára.
A Psalm of David. Give unto the LORD, O ye sons of the mighty, give unto the LORD glory and strength.
2 Fi fún Olúwa, àní ògo orúkọ rẹ̀; sin Olúwa nínú ẹwà ìwà mímọ́.
Give unto the LORD the glory due unto his name; worship the LORD in the beauty of holiness.
3 Ohùn Olúwa n ré àwọn omi kọjá; Ọlọ́run ògo sán àrá, Olúwa san ara.
The voice of the LORD is upon the waters: the God of glory thundereth, even the LORD upon many waters.
4 Ohùn Olúwa ní agbára; ohùn Olúwa kún fún ọláńlá.
The voice of the LORD is powerful; the voice of the LORD is full of majesty.
5 Ohùn Olúwa fa igi kedari; Olúwa náà ló fọ́ igi kedari Lebanoni ya.
The voice of the LORD breaketh the cedars; yea, the LORD breaketh in pieces the cedars of Lebanon.
6 Ó mú Lebanoni fo bí i ọmọ màlúù, àti Sirioni bí ọmọ àgbáǹréré.
He maketh them also to skip like a calf; Lebanon and Sirion like a young wild-ox.
7 Ohùn Olúwa ń ya bí ọwọ́ iná mọ̀nà.
The voice of the LORD cleaveth the flames of fire.
8 Ohùn Olúwa ń mi aginjù. Olúwa mi aginjù Kadeṣi.
The voice of the LORD shaketh the wilderness; the LORD shaketh the wilderness of Kadesh.
9 Ohùn Olúwa ní ó lọ igi óákù, ó n mú abo àgbọ̀nrín bí, ó sì bọ́ igi igbó sí ìhòhò. Àti nínú tẹmpili rẹ̀ gbogbo ohùn wí pé, “Ògo!”
The voice of the LORD maketh the hinds to calve, and strippeth the forests bare: and in his temple every thing saith, Glory.
10 Olúwa jókòó, Ó sì jẹ ọba lórí ìṣàn omi; Olúwa jókòó lórí ìtẹ́ gẹ́gẹ́ bí Ọba títí láéláé.
The LORD sat [as king] at the Flood; yea, the LORD sitteth as king for ever.
11 Kí Olúwa fi agbára fún àwọn ènìyàn rẹ̀; bùkún àwọn ènìyàn rẹ̀ pẹ̀lú àlàáfíà.
The LORD will give strength unto his people; the LORD will bless his people with peace.

< Psalms 29 >