< Psalms 29 >

1 Saamu ti Dafidi. Ẹ fi fún Olúwa, ẹ̀yin ẹ̀dá ọ̀run, ẹ fi fún Olúwa, ògo àti alágbára.
A PSALM OF DAVID. Ascribe to YHWH, you sons of the mighty, Ascribe to YHWH glory and strength.
2 Fi fún Olúwa, àní ògo orúkọ rẹ̀; sin Olúwa nínú ẹwà ìwà mímọ́.
Ascribe to YHWH the glory of His Name, Bow yourselves to YHWH, In the beauty of holiness.
3 Ohùn Olúwa n ré àwọn omi kọjá; Ọlọ́run ògo sán àrá, Olúwa san ara.
The voice of YHWH [is] on the waters, The God of glory has thundered, YHWH [is] on many waters.
4 Ohùn Olúwa ní agbára; ohùn Olúwa kún fún ọláńlá.
The voice of YHWH [is] with power, The voice of YHWH [is] with majesty,
5 Ohùn Olúwa fa igi kedari; Olúwa náà ló fọ́ igi kedari Lebanoni ya.
The voice of YHWH [is] shattering cedars, Indeed, YHWH shatters the cedars of Lebanon.
6 Ó mú Lebanoni fo bí i ọmọ màlúù, àti Sirioni bí ọmọ àgbáǹréré.
And He causes them to skip as a calf, Lebanon and Sirion as a son of Reems,
7 Ohùn Olúwa ń ya bí ọwọ́ iná mọ̀nà.
The voice of YHWH is hewing fiery flames,
8 Ohùn Olúwa ń mi aginjù. Olúwa mi aginjù Kadeṣi.
The voice of YHWH pains a wilderness, YHWH pains the wilderness of Kadesh.
9 Ohùn Olúwa ní ó lọ igi óákù, ó n mú abo àgbọ̀nrín bí, ó sì bọ́ igi igbó sí ìhòhò. Àti nínú tẹmpili rẹ̀ gbogbo ohùn wí pé, “Ògo!”
The voice of YHWH pains the oaks, And makes bare the forests, And in His temple everyone says, “Glory!”
10 Olúwa jókòó, Ó sì jẹ ọba lórí ìṣàn omi; Olúwa jókòó lórí ìtẹ́ gẹ́gẹ́ bí Ọba títí láéláé.
YHWH has sat on the flood, And YHWH sits [as] king for all time,
11 Kí Olúwa fi agbára fún àwọn ènìyàn rẹ̀; bùkún àwọn ènìyàn rẹ̀ pẹ̀lú àlàáfíà.
YHWH gives strength to His people, YHWH blesses His people with peace!

< Psalms 29 >