< Psalms 29 >

1 Saamu ti Dafidi. Ẹ fi fún Olúwa, ẹ̀yin ẹ̀dá ọ̀run, ẹ fi fún Olúwa, ògo àti alágbára.
“A psalm of David.” Ascribe unto the Lord, O ye sons of the mighty, ascribe unto the Lord glory and strength.
2 Fi fún Olúwa, àní ògo orúkọ rẹ̀; sin Olúwa nínú ẹwà ìwà mímọ́.
Ascribe unto the Lord the glory of his name; bow down to the Lord in the beauty of holiness.
3 Ohùn Olúwa n ré àwọn omi kọjá; Ọlọ́run ògo sán àrá, Olúwa san ara.
The voice of the Lord is upon the waters; the God of glory thundereth, the Lord—upon mighty waters.
4 Ohùn Olúwa ní agbára; ohùn Olúwa kún fún ọláńlá.
The voice of the Lord [resoundeth] with power; the voice of the Lord [resoundeth] with majesty.
5 Ohùn Olúwa fa igi kedari; Olúwa náà ló fọ́ igi kedari Lebanoni ya.
The voice of the Lord breaketh in pieces the cedars; yea, the Lord shivereth the cedars of Lebanon;
6 Ó mú Lebanoni fo bí i ọmọ màlúù, àti Sirioni bí ọmọ àgbáǹréré.
And he maketh them skip like a calf; Lebanon and Siryon like young reems.
7 Ohùn Olúwa ń ya bí ọwọ́ iná mọ̀nà.
The voice of the Lord heweth out flames of fire.
8 Ohùn Olúwa ń mi aginjù. Olúwa mi aginjù Kadeṣi.
The voice of the Lord shaketh the wilderness; the Lord shaketh the wilderness of Kadesh.
9 Ohùn Olúwa ní ó lọ igi óákù, ó n mú abo àgbọ̀nrín bí, ó sì bọ́ igi igbó sí ìhòhò. Àti nínú tẹmpili rẹ̀ gbogbo ohùn wí pé, “Ògo!”
The voice of the Lord causeth the hinds to start, and maketh bare forests: and in his temple every thing speaketh [of his] glory.
10 Olúwa jókòó, Ó sì jẹ ọba lórí ìṣàn omi; Olúwa jókòó lórí ìtẹ́ gẹ́gẹ́ bí Ọba títí láéláé.
The Lord sat [enthroned] at the flood: and the Lord will sit as King for ever.
11 Kí Olúwa fi agbára fún àwọn ènìyàn rẹ̀; bùkún àwọn ènìyàn rẹ̀ pẹ̀lú àlàáfíà.
The Lord will give strength unto his people: the Lord will bless his people with peace.

< Psalms 29 >