< Psalms 29 >
1 Saamu ti Dafidi. Ẹ fi fún Olúwa, ẹ̀yin ẹ̀dá ọ̀run, ẹ fi fún Olúwa, ògo àti alágbára.
A Psalm of David [on the occasion] of the solemn assembly of the Tabernacle. Bring to the Lord, ye sons of God, bring to the Lord young rams; bring to the Lord glory and honour.
2 Fi fún Olúwa, àní ògo orúkọ rẹ̀; sin Olúwa nínú ẹwà ìwà mímọ́.
Bring to the Lord glory, [due] to his name; worship the lord in his holy court.
3 Ohùn Olúwa n ré àwọn omi kọjá; Ọlọ́run ògo sán àrá, Olúwa san ara.
The voice of the Lord is upon the waters: the God of glory has thundered: the Lord is upon many waters.
4 Ohùn Olúwa ní agbára; ohùn Olúwa kún fún ọláńlá.
The voice of the Lord is mighty; the voice of the Lord is full of majesty.
5 Ohùn Olúwa fa igi kedari; Olúwa náà ló fọ́ igi kedari Lebanoni ya.
[There is] the voice of the Lord who breaks the cedars; the Lord will break the cedars of Libanus.
6 Ó mú Lebanoni fo bí i ọmọ màlúù, àti Sirioni bí ọmọ àgbáǹréré.
And he will beat them small, [even] Libanus itself, like a calf; and the beloved one is as a young unicorn.
7 Ohùn Olúwa ń ya bí ọwọ́ iná mọ̀nà.
[There is] a voice of the Lord who divides a flame of fire.
8 Ohùn Olúwa ń mi aginjù. Olúwa mi aginjù Kadeṣi.
A voice of the Lord who shakes the wilderness; the Lord will shake the wilderness of Cades.
9 Ohùn Olúwa ní ó lọ igi óákù, ó n mú abo àgbọ̀nrín bí, ó sì bọ́ igi igbó sí ìhòhò. Àti nínú tẹmpili rẹ̀ gbogbo ohùn wí pé, “Ògo!”
The voice of the Lord strengthens the hinds, and will uncover the thickets: and in his temple every one speaks [of his] glory.
10 Olúwa jókòó, Ó sì jẹ ọba lórí ìṣàn omi; Olúwa jókòó lórí ìtẹ́ gẹ́gẹ́ bí Ọba títí láéláé.
The Lord will dwell on the waterflood: and the Lord will sit a king for ever.
11 Kí Olúwa fi agbára fún àwọn ènìyàn rẹ̀; bùkún àwọn ènìyàn rẹ̀ pẹ̀lú àlàáfíà.
The Lord will give strength to his people; the Lord will bless his people with peace.