< Psalms 28 >

1 Ti Dafidi. Ìwọ Olúwa, mo ké pe àpáta mi. Má ṣe kọ etí dídi sí mi. Tí ìwọ bá dákẹ́ sí mi, èmí yóò dàbí àwọn tí ó lọ sí ọ̀gbun.
Psalm Dawidowy. Do ciebie, Panie! wołam, skało moja! nie milcz na wołanie moje, bym snać, jeźli mi się nie ozwiesz, nie stał się podobnym zstępującym do grobu.
2 Gbọ́ ohùn ẹ̀bẹ̀ mi fún àánú, bí mo ṣe ń ké pè ọ́ fún ìrànlọ́wọ́, bí mo ṣe gbé àwọn ọwọ́ mi sókè sí Ibi Mímọ́ rẹ Jùlọ.
Wysłuchajże głos próśb moich, gdy wołam do ciebie, gdy podnoszę ręce moje do świątnicy świętej twojej.
3 Má ṣe fà mí lọ pẹ̀lú ènìyàn búburú àti, pẹ̀lú àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀, tí ń sọ̀rọ̀ àlàáfíà sí aládùúgbò wọn ṣùgbọ́n tí ìwà ìkà ń bẹ nínú wọn.
Nie zagarniaj mię z niezbożnymi, i z czyniącymi nieprawość, którzy mówią o pokoju z bliźnimi swymi a myślą złe w sercach swoich.
4 San ẹ̀san wọn gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ wọn àti fún iṣẹ́ ibi wọn; gba ẹ̀san wọn gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ ọwọ́ wọn; kí o sì san ẹ̀san wọn bí ó ti tọ́.
Oddajże im według spraw ich i według złych uczynków ich; według pracy rąk ich oddaj im, oddaj im zapłatę ich.
5 Nítorí pé wọn kò ka iṣẹ́ Olúwa sí, tàbí àwọn iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀ òun ó rún wọn wọlẹ̀ kì yóò sì gbé wọn ró mọ́.
Albowiem nie zrozumiewają spraw Pańskich, ani uczynków rąk jego; przetoż ich popsuje, a nie pobuduje ich.
6 Alábùkún fún ni Olúwa! Nítorí pé ó ti gbọ́ ohùn ẹ̀bẹ̀ mi.
Błogosławiony Pan; albowiem wysłuchał głos próśb moich.
7 Olúwa ni agbára mi àti asà mi; nínú rẹ̀ ni mo gbẹ́kẹ̀lé; àní, ó sì ràn mí lọ́wọ́. Ọkàn mi sì gbé sókè fún ayọ̀ àní pẹ̀lú orin mi mo fi ọpẹ́ fún un.
Pan jest mocą moją i tarczą moją, w nim, nadzieję ma serce moje, a jestem poratowany; przetoż się rozweseliło serce moje, a pieśnią moją chwalić go będę.
8 Olúwa ni agbára àwọn ènìyàn rẹ̀ òun ni odi ìgbàlà àwọn ẹni àmì òróró rẹ̀.
Pan jest mocą swych, i mocą zbawienia pomazańca swego on jest.
9 Ìwọ gba àwọn ènìyàn rẹ là, kí o sì bùkún àwọn ajogún rẹ; di olùṣọ́-àgùntàn wọn, kí o sì gbé wọn lékè títí ayérayé.
Zbaw lud twój, Panie! a błogosław dziedzictwu twemu, i paś ich, i wywyższaj aż na wieki.

< Psalms 28 >