< Psalms 28 >
1 Ti Dafidi. Ìwọ Olúwa, mo ké pe àpáta mi. Má ṣe kọ etí dídi sí mi. Tí ìwọ bá dákẹ́ sí mi, èmí yóò dàbí àwọn tí ó lọ sí ọ̀gbun.
Ég hrópa til þín um hjálp, Drottinn, því að þú ert klettur hjálpræðis míns. Ef þú hjálpaðir ekki væri úti um mig. Framundan væri ekkert nema dauðinn.
2 Gbọ́ ohùn ẹ̀bẹ̀ mi fún àánú, bí mo ṣe ń ké pè ọ́ fún ìrànlọ́wọ́, bí mo ṣe gbé àwọn ọwọ́ mi sókè sí Ibi Mímọ́ rẹ Jùlọ.
Drottinn, ég lyfti höndum til himins og ákalla þig um hjálp. Ó, heyr þú grátbeiðni mína!
3 Má ṣe fà mí lọ pẹ̀lú ènìyàn búburú àti, pẹ̀lú àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀, tí ń sọ̀rọ̀ àlàáfíà sí aládùúgbò wọn ṣùgbọ́n tí ìwà ìkà ń bẹ nínú wọn.
Drottinn, refsaðu mér ekki ásamt illgjörðamönnunum, þeim sem sitja á svikráðum við nágranna sína.
4 San ẹ̀san wọn gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ wọn àti fún iṣẹ́ ibi wọn; gba ẹ̀san wọn gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ ọwọ́ wọn; kí o sì san ẹ̀san wọn bí ó ti tọ́.
Refsaðu þeim eins og rétt er. Illvirki þeirra eiga skilið réttlátan dóm.
5 Nítorí pé wọn kò ka iṣẹ́ Olúwa sí, tàbí àwọn iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀ òun ó rún wọn wọlẹ̀ kì yóò sì gbé wọn ró mọ́.
Þeir hugsa ekkert um Guð, sköpun hans og verk. Þess vegna mun Guð ryðja þeim úr vegi, rífa þá eins og ónýtt hús sem ekki verður endurreist.
6 Alábùkún fún ni Olúwa! Nítorí pé ó ti gbọ́ ohùn ẹ̀bẹ̀ mi.
Lofaður sé Drottinn! Hann heyrði grátbeiðni mína!
7 Olúwa ni agbára mi àti asà mi; nínú rẹ̀ ni mo gbẹ́kẹ̀lé; àní, ó sì ràn mí lọ́wọ́. Ọkàn mi sì gbé sókè fún ayọ̀ àní pẹ̀lú orin mi mo fi ọpẹ́ fún un.
Hann er styrkur minn, skjól mitt gegn öllum árásum. Honum treysti ég og hann hjálpaði mér. Gleðin svellur í brjósti mér og brýst út í lofgjörð til hans!
8 Olúwa ni agbára àwọn ènìyàn rẹ̀ òun ni odi ìgbàlà àwọn ẹni àmì òróró rẹ̀.
Drottinn verndar sitt fólk og veitir konungi sínum sigur.
9 Ìwọ gba àwọn ènìyàn rẹ là, kí o sì bùkún àwọn ajogún rẹ; di olùṣọ́-àgùntàn wọn, kí o sì gbé wọn lékè títí ayérayé.
Stattu vörð um þjóð þína, Drottinn! Vernda og blessa þitt útvalda fólk. Eins og fjárhirðir leiðir sauði sína, þá leið og vernda þjóð þína að eilífu.