< Psalms 28 >

1 Ti Dafidi. Ìwọ Olúwa, mo ké pe àpáta mi. Má ṣe kọ etí dídi sí mi. Tí ìwọ bá dákẹ́ sí mi, èmí yóò dàbí àwọn tí ó lọ sí ọ̀gbun.
De David. Je crie vers toi, ô Éternel! Mon rocher, ne sois pas sourd à ma prière, De peur que, si tu t'éloignes sans me répondre, Je ne devienne semblable à ceux qui descendent dans la tombe.
2 Gbọ́ ohùn ẹ̀bẹ̀ mi fún àánú, bí mo ṣe ń ké pè ọ́ fún ìrànlọ́wọ́, bí mo ṣe gbé àwọn ọwọ́ mi sókè sí Ibi Mímọ́ rẹ Jùlọ.
Écoute ma voix suppliante, quand je crie vers toi, Quand j'élève mes mains vers ton sanctuaire.
3 Má ṣe fà mí lọ pẹ̀lú ènìyàn búburú àti, pẹ̀lú àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀, tí ń sọ̀rọ̀ àlàáfíà sí aládùúgbò wọn ṣùgbọ́n tí ìwà ìkà ń bẹ nínú wọn.
Ne m'entraîne pas dans la ruine des méchants Et des ouvriers d'iniquité, Qui parlent de paix avec leur prochain. Quand la malice est dans leur coeur.
4 San ẹ̀san wọn gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ wọn àti fún iṣẹ́ ibi wọn; gba ẹ̀san wọn gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ ọwọ́ wọn; kí o sì san ẹ̀san wọn bí ó ti tọ́.
Traite-les selon leurs oeuvres, Selon la méchanceté de leurs actions; Traite-les selon l'ouvrage de leurs mains. Rends-leur ce qu'ils ont mérité!
5 Nítorí pé wọn kò ka iṣẹ́ Olúwa sí, tàbí àwọn iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀ òun ó rún wọn wọlẹ̀ kì yóò sì gbé wọn ró mọ́.
Puisqu'ils ne prennent pas garde aux oeuvres de l'Éternel, Ni à l'ouvrage de ses mains, Il les détruira, et il ne les relèvera point!
6 Alábùkún fún ni Olúwa! Nítorí pé ó ti gbọ́ ohùn ẹ̀bẹ̀ mi.
Béni soit l'Éternel! Car il a entendu ma voix suppliante.
7 Olúwa ni agbára mi àti asà mi; nínú rẹ̀ ni mo gbẹ́kẹ̀lé; àní, ó sì ràn mí lọ́wọ́. Ọkàn mi sì gbé sókè fún ayọ̀ àní pẹ̀lú orin mi mo fi ọpẹ́ fún un.
L'Éternel est ma force et mon bouclier. Mon coeur s'est confié en lui, et j'ai été secouru; Aussi mon coeur est-il plein d'allégresse, Et je loue l'Éternel dans mes cantiques.
8 Olúwa ni agbára àwọn ènìyàn rẹ̀ òun ni odi ìgbàlà àwọn ẹni àmì òróró rẹ̀.
L'Éternel est la force des siens; Il est un rempart de salut pour son oint.
9 Ìwọ gba àwọn ènìyàn rẹ là, kí o sì bùkún àwọn ajogún rẹ; di olùṣọ́-àgùntàn wọn, kí o sì gbé wọn lékè títí ayérayé.
Sauve ton peuple, et bénis ton héritage! Sois leur berger, et soutiens-les éternellement.

< Psalms 28 >