< Psalms 27 >

1 Ti Dafidi. Olúwa ni ìmọ́lẹ̀ mi àti ìgbàlà mi; ta ni èmi yóò bẹ̀rù? Olúwa ni ibi ìsádi ẹ̀mí mi, ẹ̀rù ta ni yóò bà mí?
Dawut yazghan küy: — Perwerdigar méning nurum we nijatliqimdur; Men yene kimdin qorqay? Perwerdigar hayatimning qorghinidur; Men kimning aldida titrey?
2 Nígbà tí àwọn ènìyàn búburú kọjú ìjà sí mi láti jẹ ẹran-ara mi, àní àwọn ọ̀tá mi àti àwọn abínúkú mi, wọn yóò kọsẹ̀, wọn yóò sì ṣubú.
Yamanliq qilghuchilar «Uning etlirini yeyli» dep manga hujum qilghanda, Reqiblirim, düshmenlirim manga yéqinlashqanda, Putliship, yiqildi ular.
3 Bí ọmọ-ogun tilẹ̀ yí mi ká tí wọ́n sì dìde sí mi, ọkàn mi kì yóò bẹ̀rù; bí ogun tilẹ̀ dìde sí mi, nínú èyí ni ọkàn mi yóò le.
Zor qoshun bargah qurup méni qorshawgha alsimu, Qelbimde héch qorqunch yoq; Manga urush qozghisimu, yenila xatirjem turiwérimen.
4 Ohun kan ni mo béèrè lọ́dọ̀ Olúwa, òhun ni èmi yóò máa wá kiri: kí èmi kí ó le wà ní ilé Olúwa ní ọjọ́ ayé mi gbogbo, kí èmi: kí ó le kíyèsi ẹwà Olúwa, kí èmi kí ó sì máa wà ní tẹmpili rẹ̀.
Perwerdigardin birla nersini tilep keldim; Men shuninggha intilimektimenki: — Ömür boyi Perwerdigarning öyide bolsam, Perwerdigarning güzellikige qarap yürsem, Uning ibadetxanisida turup, yéteklishige muyesser bolsam, deymen.
5 Nítorí pé ní ìgbà ìpọ́njú òun yóò pa mí mọ́ nínú àgọ́ rẹ̀; níbi ìkọ̀kọ̀ àgọ́ rẹ̀ ni òun yóò pa mí mọ́; yóò sì gbé mi sókè lórí àpáta.
Béshimgha kün chüshkende, U méni sayiwini astigha alidu; Méni chédirining ichide aman saqlap yoshuruwalidu. U méni uyultash üstige muqim turghuzidu.
6 Ní ìsinsin yìí, a ti gbé orí mi sókè ga ju ti àwọn ọ̀tá mi lọ tí ó yí mí ká; èmi yóò rú ẹbọ nínú àgọ́ rẹ, ẹbọ ariwo àti ti ayọ̀; èmi yóò kọrin àní orin dídùn sí Olúwa.
Shunga hazir etrapimdiki düshmenlirim aldida béshim yuqiri kötürülidu. Uning muqeddes chédirida tentene qilip qurbanliqlar sunimen; Naxsha-küyler éytimen, munajatlarni éytimen Perwerdigargha!
7 Gbọ́ ohùn mi nígbà tí ẹ̀mí bá à ń pè, Olúwa, ṣe àánú fún mi kí o sì dá mi lóhùn,
Nida qilghinimda awazimni anglighaysen, i Perwerdigar; Manga méhir-shepqet körsitip, ijabet qilghaysen.
8 Ọkàn mi wí pé, “Wá ojú u rẹ̀!” Ojú rẹ, Olúwa, ni ti èmí ń wá.
Öz könglüm: «Uning didarini izdenglar!» deydu; Didaringni, i Perwerdigar, özüm izdeymen.
9 Má ṣe fi ojú rẹ pamọ́ kúrò lọ́dọ̀ mi, má ṣe fi ìbínú sá ìránṣẹ́ rẹ tì; ìwọ tí o ti jẹ́ olùrànlọ́wọ́ mi, Má ṣe fi mí sílẹ̀, má sì ṣe kọ̀ mí, háà! Ọlọ́run ìgbàlà mi.
Mendin Özüngni qachurmighaysen! Ghezeplen’gende qulungni néri qoghlimighaysen; Sen méningdin yardimingni ayimay kelding; Sen mendin ayrilmighaysen, méni tashliwetmigeysen, i Nijatkarim Xuda!
10 Bí ìyá àti baba bá kọ̀ mí sílẹ̀, Olúwa yóò tẹ́wọ́ gbà mí.
Ata-anam méni tashliwetsimu, Perwerdigar méni quchiqigha alidu.
11 Kọ́ mi ní ọ̀nà rẹ, Olúwa, kí o sì sìn mi lọ sí ọ̀nà tí ó tẹ́jú nítorí àwọn ọ̀tá mi.
Manga Öz yolungni ögetkeysen, i Perwerdigar; Küshendilirim [paylap yürmekte], Méni tüz yolgha bashlighaysen.
12 Má ṣe fi mí lé ìfẹ́ àwọn ọ̀tá mi lọ́wọ́, nítorí àwọn ẹlẹ́rìí èké ti dìde sí mi, wọ́n sì mí ìmí ìkà.
Méni reqiblirimning meylige tapshurmighaysen, Chünki manga qara chaplashmaqchi bolghan yalghanchilar xéli köptur, Ularning nepeslirimu zorawanliqtur.
13 Èmi ní ìgbàgbọ́ pé, èmi yóò rí ìre Olúwa ní ilẹ̀ alààyè.
Ah, Perwerdigarning méhribanliqini tiriklerning zéminide körüshke közüm yetmigen bolsa...!
14 Dúró de Olúwa; kí ó jẹ alágbára, kí o sì mú ọkàn le àní dúró de Olúwa.
Perwerdigarni telmürüp kütkin! Jigerlik bol, qelbing merdane bolsun! Shundaq qil, Perwerdigarni telmürüp kütkin!

< Psalms 27 >