< Psalms 27 >

1 Ti Dafidi. Olúwa ni ìmọ́lẹ̀ mi àti ìgbàlà mi; ta ni èmi yóò bẹ̀rù? Olúwa ni ibi ìsádi ẹ̀mí mi, ẹ̀rù ta ni yóò bà mí?
En Psalm Davids. Herren är mitt ljus och min helsa; för hvem skall jag frukta mig? Herren är mins lifs kraft; för hvem skulle jag grufva mig?
2 Nígbà tí àwọn ènìyàn búburú kọjú ìjà sí mi láti jẹ ẹran-ara mi, àní àwọn ọ̀tá mi àti àwọn abínúkú mi, wọn yóò kọsẹ̀, wọn yóò sì ṣubú.
Derföre, om de onde mine motståndare och fiender till mig vilja, till att fräta mitt kött, måste de stöta sig och falla.
3 Bí ọmọ-ogun tilẹ̀ yí mi ká tí wọ́n sì dìde sí mi, ọkàn mi kì yóò bẹ̀rù; bí ogun tilẹ̀ dìde sí mi, nínú èyí ni ọkàn mi yóò le.
Om än en här lade sig emot mig, så fruktade sig ändå mitt hjerta intet; om en strid hofve sig upp emot mig, så förlåter jag mig uppå honom.
4 Ohun kan ni mo béèrè lọ́dọ̀ Olúwa, òhun ni èmi yóò máa wá kiri: kí èmi kí ó le wà ní ilé Olúwa ní ọjọ́ ayé mi gbogbo, kí èmi: kí ó le kíyèsi ẹwà Olúwa, kí èmi kí ó sì máa wà ní tẹmpili rẹ̀.
Ett beder jag af Herranom, det hade jag gerna; att jag i Herrans hus blifva må i alla mina lifsdagar, till att skåda den sköna Herrans Gudstjenst, och besöka hans tempel.
5 Nítorí pé ní ìgbà ìpọ́njú òun yóò pa mí mọ́ nínú àgọ́ rẹ̀; níbi ìkọ̀kọ̀ àgọ́ rẹ̀ ni òun yóò pa mí mọ́; yóò sì gbé mi sókè lórí àpáta.
Ty han öfvertäcker mig i sine hyddo i ondom tid; han förgömmer mig hemliga i sitt tjäll, och upphöjer mig på ene klippo;
6 Ní ìsinsin yìí, a ti gbé orí mi sókè ga ju ti àwọn ọ̀tá mi lọ tí ó yí mí ká; èmi yóò rú ẹbọ nínú àgọ́ rẹ, ẹbọ ariwo àti ti ayọ̀; èmi yóò kọrin àní orin dídùn sí Olúwa.
Och skall nu upphöja mitt hufvud öfver mina fiendar, som omkring mig äro; så vill jag i hans hyddo lof offra; jag vill sjunga och lofsäga Herranom.
7 Gbọ́ ohùn mi nígbà tí ẹ̀mí bá à ń pè, Olúwa, ṣe àánú fún mi kí o sì dá mi lóhùn,
Herre, hör mina röst, när jag ropar; var mig nådelig, och hör mig.
8 Ọkàn mi wí pé, “Wá ojú u rẹ̀!” Ojú rẹ, Olúwa, ni ti èmí ń wá.
Mitt hjerta håller dig ditt ord före: I skolen söka mitt ansigte; derföre söker jag ock, Herre, ditt ansigte.
9 Má ṣe fi ojú rẹ pamọ́ kúrò lọ́dọ̀ mi, má ṣe fi ìbínú sá ìránṣẹ́ rẹ tì; ìwọ tí o ti jẹ́ olùrànlọ́wọ́ mi, Má ṣe fi mí sílẹ̀, má sì ṣe kọ̀ mí, háà! Ọlọ́run ìgbàlà mi.
Fördölj icke ditt ansigte för mig, och bortdrif icke din tjenare i vredene; ty du äst min hjelp; öfvergif mig icke, och drag icke handena ifrå mig, Gud, min salighet.
10 Bí ìyá àti baba bá kọ̀ mí sílẹ̀, Olúwa yóò tẹ́wọ́ gbà mí.
Ty min fader och min moder öfvergifva mig; men Herren upptager mig.
11 Kọ́ mi ní ọ̀nà rẹ, Olúwa, kí o sì sìn mi lọ sí ọ̀nà tí ó tẹ́jú nítorí àwọn ọ̀tá mi.
Herre, visa mig din väg, och led mig på den rätta stigen, för mina fiendars skull.
12 Má ṣe fi mí lé ìfẹ́ àwọn ọ̀tá mi lọ́wọ́, nítorí àwọn ẹlẹ́rìí èké ti dìde sí mi, wọ́n sì mí ìmí ìkà.
Gif mig icke uti mina fiendars vilja; ty falsk vittne stå emot mig, och göra mig orätt skamlöst.
13 Èmi ní ìgbàgbọ́ pé, èmi yóò rí ìre Olúwa ní ilẹ̀ alààyè.
Men jag tror dock, att jag se skall Herrans goda, uti de lefvandes lande.
14 Dúró de Olúwa; kí ó jẹ alágbára, kí o sì mú ọkàn le àní dúró de Olúwa.
Förbida Herran; var tröst och oförfärad, och förbida Herran.

< Psalms 27 >