< Psalms 27 >
1 Ti Dafidi. Olúwa ni ìmọ́lẹ̀ mi àti ìgbàlà mi; ta ni èmi yóò bẹ̀rù? Olúwa ni ibi ìsádi ẹ̀mí mi, ẹ̀rù ta ni yóò bà mí?
Dāvida dziesma. Tas Kungs ir mans gaišums un mana pestīšana, no kā man bīties? Tas Kungs ir manas dzīvības stiprums, no kā man baiļoties?
2 Nígbà tí àwọn ènìyàn búburú kọjú ìjà sí mi láti jẹ ẹran-ara mi, àní àwọn ọ̀tá mi àti àwọn abínúkú mi, wọn yóò kọsẹ̀, wọn yóò sì ṣubú.
Kad ļaunie, mani pretinieki un ienaidnieki, uz mani laužas manu miesu ēst, tad tiem būs piedauzīties un krist.
3 Bí ọmọ-ogun tilẹ̀ yí mi ká tí wọ́n sì dìde sí mi, ọkàn mi kì yóò bẹ̀rù; bí ogun tilẹ̀ dìde sí mi, nínú èyí ni ọkàn mi yóò le.
Kad arī pulki pret mani apmetās, taču mana sirds nebīstas; kad karš pret mani ceļas, tad es paļaujos uz Viņu.
4 Ohun kan ni mo béèrè lọ́dọ̀ Olúwa, òhun ni èmi yóò máa wá kiri: kí èmi kí ó le wà ní ilé Olúwa ní ọjọ́ ayé mi gbogbo, kí èmi: kí ó le kíyèsi ẹwà Olúwa, kí èmi kí ó sì máa wà ní tẹmpili rẹ̀.
Vienu lietu es no Tā Kunga lūdzos, to es meklēju tikuši(mana sirds vēlēšanās), ka es varu dzīvot Tā Kunga namā visu savu mūžu, raudzīt Tā Kunga laipnību un pielūgt Viņa svētā vietā.
5 Nítorí pé ní ìgbà ìpọ́njú òun yóò pa mí mọ́ nínú àgọ́ rẹ̀; níbi ìkọ̀kọ̀ àgọ́ rẹ̀ ni òun yóò pa mí mọ́; yóò sì gbé mi sókè lórí àpáta.
Jo ļaunā dienā Viņš mani paslēpj Savā dzīvoklī Viņš mani sargā Savas telts ēnā, Viņš mani paaugstina uz akmens kalnu.
6 Ní ìsinsin yìí, a ti gbé orí mi sókè ga ju ti àwọn ọ̀tá mi lọ tí ó yí mí ká; èmi yóò rú ẹbọ nínú àgọ́ rẹ, ẹbọ ariwo àti ti ayọ̀; èmi yóò kọrin àní orin dídùn sí Olúwa.
Un nu mana galva taps paaugstināta pār maniem ienaidniekiem, kas ir ap mani; un es upurēšu Viņa teltī teikšanas upurus, es dziedāšu un slavēšu To Kungu.
7 Gbọ́ ohùn mi nígbà tí ẹ̀mí bá à ń pè, Olúwa, ṣe àánú fún mi kí o sì dá mi lóhùn,
Klausi, ak Kungs, manu balsi; kad es saucu, tad žēlo mani un atbildi man.
8 Ọkàn mi wí pé, “Wá ojú u rẹ̀!” Ojú rẹ, Olúwa, ni ti èmí ń wá.
Mana sirds saka uz tevi: „Meklējiet Manu vaigu!“Es meklēju, Kungs, Tavu vaigu.
9 Má ṣe fi ojú rẹ pamọ́ kúrò lọ́dọ̀ mi, má ṣe fi ìbínú sá ìránṣẹ́ rẹ tì; ìwọ tí o ti jẹ́ olùrànlọ́wọ́ mi, Má ṣe fi mí sílẹ̀, má sì ṣe kọ̀ mí, háà! Ọlọ́run ìgbàlà mi.
Neapslēp Savu vaigu priekš manis, neatstum Savu kalpu dusmībā, - Tu esi mans palīgs; neatmet mani un neatstāj mani, ak Dievs, mans Pestītājs.
10 Bí ìyá àti baba bá kọ̀ mí sílẹ̀, Olúwa yóò tẹ́wọ́ gbà mí.
Jo mans tēvs un mana māte mani atstājuši, bet Tas Kungs mani uzņem.
11 Kọ́ mi ní ọ̀nà rẹ, Olúwa, kí o sì sìn mi lọ sí ọ̀nà tí ó tẹ́jú nítorí àwọn ọ̀tá mi.
Māci man, Kungs, Tavu ceļu, un vadi mani uz īstenu ceļu, manu ienaidnieku dēļ.
12 Má ṣe fi mí lé ìfẹ́ àwọn ọ̀tá mi lọ́wọ́, nítorí àwọn ẹlẹ́rìí èké ti dìde sí mi, wọ́n sì mí ìmí ìkà.
Nenodod mani manu pretinieku prātam, jo viltīgi liecinieki ceļas pret mani un runā netaisnību.
13 Èmi ní ìgbàgbọ́ pé, èmi yóò rí ìre Olúwa ní ilẹ̀ alààyè.
Ja es nebūtu ticējis, ka es redzēšu Tā Kunga labumu dzīvības zemē, (tad es būtu bojā gājis).
14 Dúró de Olúwa; kí ó jẹ alágbára, kí o sì mú ọkàn le àní dúró de Olúwa.
Gaidi uz To Kungu, esi drošs un stiprs savā sirdī, un gaidi uz To Kungu.