< Psalms 27 >

1 Ti Dafidi. Olúwa ni ìmọ́lẹ̀ mi àti ìgbàlà mi; ta ni èmi yóò bẹ̀rù? Olúwa ni ibi ìsádi ẹ̀mí mi, ẹ̀rù ta ni yóò bà mí?
“Of David.” The Lord is my light and my salvation; of whom shall I be afraid? the Lord is the fortress of my life; of whom shall I have dread?
2 Nígbà tí àwọn ènìyàn búburú kọjú ìjà sí mi láti jẹ ẹran-ara mi, àní àwọn ọ̀tá mi àti àwọn abínúkú mi, wọn yóò kọsẹ̀, wọn yóò sì ṣubú.
When evil-doers come near against me to eat up my flesh, my assailants and my enemies at me: then do they stumble and fall.
3 Bí ọmọ-ogun tilẹ̀ yí mi ká tí wọ́n sì dìde sí mi, ọkàn mi kì yóò bẹ̀rù; bí ogun tilẹ̀ dìde sí mi, nínú èyí ni ọkàn mi yóò le.
If an army should encamp against me, my heart shall not fear: if war should arise against me, even then will I have trust.
4 Ohun kan ni mo béèrè lọ́dọ̀ Olúwa, òhun ni èmi yóò máa wá kiri: kí èmi kí ó le wà ní ilé Olúwa ní ọjọ́ ayé mi gbogbo, kí èmi: kí ó le kíyèsi ẹwà Olúwa, kí èmi kí ó sì máa wà ní tẹmpili rẹ̀.
One thing have I asked of the Lord, that I will seek for: that I may dwell in the house of the Lord all the days of my life, to behold the loveliness of the Lord, and to be every morning early in his temple.
5 Nítorí pé ní ìgbà ìpọ́njú òun yóò pa mí mọ́ nínú àgọ́ rẹ̀; níbi ìkọ̀kọ̀ àgọ́ rẹ̀ ni òun yóò pa mí mọ́; yóò sì gbé mi sókè lórí àpáta.
For he will hide me in his pavilion on the day of evil; he will conceal me in the secret of his tabernacle; upon a rock will he place me high.
6 Ní ìsinsin yìí, a ti gbé orí mi sókè ga ju ti àwọn ọ̀tá mi lọ tí ó yí mí ká; èmi yóò rú ẹbọ nínú àgọ́ rẹ, ẹbọ ariwo àti ti ayọ̀; èmi yóò kọrin àní orin dídùn sí Olúwa.
And now will my head be lifted up above my enemies all round about me; and I will sacrifice in his tabernacle sacrifices of joy: I will sing, and I will triumphantly play unto the Lord.
7 Gbọ́ ohùn mi nígbà tí ẹ̀mí bá à ń pè, Olúwa, ṣe àánú fún mi kí o sì dá mi lóhùn,
Hear, O Lord, my voice, [when] I call, and be gracious unto me, and answer me.
8 Ọkàn mi wí pé, “Wá ojú u rẹ̀!” Ojú rẹ, Olúwa, ni ti èmí ń wá.
Of thee, said my heart, “Seek ye my presence”: thy presence, Lord, will I seek.
9 Má ṣe fi ojú rẹ pamọ́ kúrò lọ́dọ̀ mi, má ṣe fi ìbínú sá ìránṣẹ́ rẹ tì; ìwọ tí o ti jẹ́ olùrànlọ́wọ́ mi, Má ṣe fi mí sílẹ̀, má sì ṣe kọ̀ mí, háà! Ọlọ́run ìgbàlà mi.
Hide [then] not thy face from me; reject not in anger thy servant, thou [who] hast been my help: cast me not off, nor forsake me, O God of my salvation.
10 Bí ìyá àti baba bá kọ̀ mí sílẹ̀, Olúwa yóò tẹ́wọ́ gbà mí.
For my father and my mother have forsaken me; but the Lord will take me up.
11 Kọ́ mi ní ọ̀nà rẹ, Olúwa, kí o sì sìn mi lọ sí ọ̀nà tí ó tẹ́jú nítorí àwọn ọ̀tá mi.
Point me out thy way, O Lord! and guide me on a level path, because of those that regard me enviously.
12 Má ṣe fi mí lé ìfẹ́ àwọn ọ̀tá mi lọ́wọ́, nítorí àwọn ẹlẹ́rìí èké ti dìde sí mi, wọ́n sì mí ìmí ìkà.
Give me not up to the [revengeful] desire of my assailants; for there are risen up against me false witnesses, and such as utter violence.
13 Èmi ní ìgbàgbọ́ pé, èmi yóò rí ìre Olúwa ní ilẹ̀ alààyè.
Unless I had believed to see the goodness of the Lord in the land of life—
14 Dúró de Olúwa; kí ó jẹ alágbára, kí o sì mú ọkàn le àní dúró de Olúwa.
Wait on the Lord; be strong, and let thy heart be of good courage; and only wait on the Lord.

< Psalms 27 >