< Psalms 25 >

1 Ti Dafidi. Olúwa, ìwọ ni mo gbé ọkàn mi sókè sí.
Dawut yazghan küy. Perwerdigar, jénim Sanga telmürüp qaraydu;
2 Ọlọ́run, èmi gbẹ́kẹ̀lé ọ; má ṣe jẹ́ kí ojú ó tì mí má ṣe jẹ́ kí àwọn ọ̀tá mi ó yọ̀ mí.
Sanga tayinimen, i Xudayim; Méni yerge qaritip xijalette qaldurmighaysen; We yaki düshmenlirimni üstümdin ghalib qilip shadlandurmighaysen;
3 Ẹni tí ó dúró tì ọ́ ojú kì yóò tì í, àwọn tí ń ṣẹ̀ láìnídìí ni kí ojú kí ó tì.
Berheq, Séni kütküchilerdin héchqaysisi shermende bolmas; Biraq héchbir sewebsiz xainliq qilghuchilar shermende bolidu.
4 Fi ọ̀nà rẹ hàn mí, Olúwa, kọ mi ní ipa tìrẹ;
Méni Séning izliringni bilidighan qilghaysen, i Perwerdigar; Yolliringni manga ögitip qoyghaysen.
5 ṣe amọ̀nà mi nínú òtítọ́ ọ̀ rẹ, kí o sì kọ́ mi, nítorí ìwọ ni Ọlọ́run ìgbàlà mi; ìwọ ni mo dúró tì ní gbogbo ọjọ́.
Méni heqiqitingde mangdurup, manga ögetkeysen; Chünki özüng méning nijatliqim bolghan Xudayimdursen; Men kün boyi Sanga qarap telmürimen;
6 Rántí, Olúwa àánú àti ìfẹ́ ẹ̀ rẹ̀ ńlá, torí pé wọ́n ti wà ní ìgbà àtijọ́.
Öz rehimdilliqliringni, özgermes méhirliringni yadinggha keltürgeysen, i Perwerdigar! Chünki ular ezeldin tartip bar bolup kelgendur;
7 Má ṣe rántí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ ìgbà èwe mi tàbí ìrékọjá mi; gẹ́gẹ́ bí i ìfẹ́ ẹ rẹ̀ rántí mi nítorí tí ìwọ dára, Ìwọ! Olúwa.
Méning yashliqimdiki gunahlirimni, Shundaqla itaetsizliklirimni ésingge keltürmigeysen; Özgermes muhebbiting, méhribanliqing bilen, méni ésingge keltürgeysen, i Perwerdigar;
8 Rere àti ẹni ìdúró ṣinṣin ní Olúwa: nítorí náà, ó kọ́ àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ ni ọ̀nà náà.
Perwerdigar méhriban we durustur; Shunga U gunahkarlarni durus yolgha salidu.
9 Ó ṣe amọ̀nà àwọn onírẹ̀lẹ̀ ni ohun tí ó dára, ó sì kọ́ àwọn onírẹ̀lẹ̀ ní ọ̀nà rẹ̀.
Möminlerni yaxshi-yamanni perq étishke U yétekleydu; Möminlerge Öz yolini ögitidu.
10 Gbogbo ipa ọ̀nà Olúwa ni ìfẹ́ àti òdodo tí ó dúró ṣinṣin, fún àwọn tí ó pa májẹ̀mú àti ẹ̀rí rẹ̀ mọ́.
Uning ehdisi we höküm-guwahlirini tutqanlarning hemmisige nisbeten, Perwerdigarning barliq yolliri özgermes muhebbet we heqiqettur.
11 Nítorí orúkọ rẹ, Olúwa, dárí ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ mi jì mí, nítorí tí ó tóbi.
Öz naming üchün, i Perwerdigar, Qebihlikim intayin éghir bolsimu, Sen uni kechüriwetkensen.
12 Àwọn wo ni ó bẹ̀rù Olúwa? Yóò kọ́ wọn ní ọ̀nà èyí tí wọn yóò yàn.
Kimki Perwerdigardin eymense, Xuda Özi tallighan yolda uninggha [heqiqetni] ögitidu;
13 Wọn yóò lo ọjọ́ wọn nínú àlàáfíà, àwọn ọmọ wọn yóò sì gba ilẹ̀ náà.
Uning jéni azade-yaxshiliqta yashaydu, Uning nesli yer yüzige miras bolidu.
14 Olúwa fi ọkàn tán, àwọn tí o bẹ̀rù u rẹ̀; ó sọ májẹ̀mú rẹ̀ di mí mọ̀ fún wọn.
Perwerdigar Özidin eyminidighanlar bilen sirdashtur; U ulargha Öz ehdisini körsitip béridu.
15 Ojú mi gbé sókè sọ́dọ̀ Olúwa, nítorí pé yóò yọ ẹsẹ̀ mi kúrò nínú àwọ̀n náà.
Méning közlirim hemishe Perwerdigargha tikilip qaraydu; Chünki U putlirimni tordin chiqiriwétidu.
16 Yípadà sí mi, kí o sì ṣe oore fún mi; nítorí pé mo nìkan wà, mo sì di olùpọ́njú.
Manga qarap méhir-shepqet körsetkeysen; Chünki men ghéribane, derdmendurmen.
17 Tì mí lẹ́yìn kúrò nínú ìpọ́njú àyà mi; kí o sì fà mí yọ kúrò nínú ìpọ́njú mi.
Könglümning azarliri köpiyip ketti; Méni basqan qismaqlardin chiqarghaysen.
18 Kíyèsi ìjìyà àti wàhálà mi, kí o sì dárí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ mi jì.
Derdlirimni, azablirimni neziringge alghin, Barliq gunahlirimni kechürgeysen!
19 Kíyèsi ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ọ̀tá mi, tí wọn kórìíra mi pẹ̀lú ìwà ìkà wọn.
Méning düshmenlirimni neziringge alghin, Chünki ular köptur; Ular manga chongqur öchmenlik bilen nepretlinidu.
20 Pa ọkàn mi mọ́, kí o sì gbà mí sílẹ̀; má ṣe jẹ́ kí a fi mí sínú ìtìjú, nítorí pé ìwọ ni ibi ìsádi mi.
Jénimni saqlighaysen, méni qutquzghaysen; Méni shermendilikte qaldurmighaysen; Chünki men Séni bashpanahim qildim.
21 Jẹ́ kí òtítọ́ inú àti ìdúró ṣinṣin kí ó pa mí mọ́; nítorí pé mo dúró tì ọ́.
Köngül sapliqi we durusluq méni qoghdighay; Chünki men Sanga ümid baghlap kütüwatimen.
22 Ra Israẹli padà, Ìwọ Ọlọ́run, nínú gbogbo ìṣòro rẹ̀!
I Xuda, Israilni barliq külpetliridin qutquzup hörlükke chiqarghaysen!

< Psalms 25 >