< Psalms 25 >
1 Ti Dafidi. Olúwa, ìwọ ni mo gbé ọkàn mi sókè sí.
Av David. Till dig, HERRE, upplyfter jag min själ.
2 Ọlọ́run, èmi gbẹ́kẹ̀lé ọ; má ṣe jẹ́ kí ojú ó tì mí má ṣe jẹ́ kí àwọn ọ̀tá mi ó yọ̀ mí.
Min Gud, på dig förtröstar jag; låt mig icke komma på skam, låt icke mina fiender fröjda sig över mig.
3 Ẹni tí ó dúró tì ọ́ ojú kì yóò tì í, àwọn tí ń ṣẹ̀ láìnídìí ni kí ojú kí ó tì.
Nej, ingen kommer på skam, som förbidar dig; på skam kommer de som, utan sak, handla trolöst.
4 Fi ọ̀nà rẹ hàn mí, Olúwa, kọ mi ní ipa tìrẹ;
HERRE, kungör mig dina vägar, lär mig dina stigar.
5 ṣe amọ̀nà mi nínú òtítọ́ ọ̀ rẹ, kí o sì kọ́ mi, nítorí ìwọ ni Ọlọ́run ìgbàlà mi; ìwọ ni mo dúró tì ní gbogbo ọjọ́.
Led mig i din sanning, och lär mig, ty du är min frälsnings Gud; dig förbidar jag alltid.
6 Rántí, Olúwa àánú àti ìfẹ́ ẹ̀ rẹ̀ ńlá, torí pé wọ́n ti wà ní ìgbà àtijọ́.
Tänk, HERRE, på din barmhärtighet och din nåd, ty de äro av evighet.
7 Má ṣe rántí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ ìgbà èwe mi tàbí ìrékọjá mi; gẹ́gẹ́ bí i ìfẹ́ ẹ rẹ̀ rántí mi nítorí tí ìwọ dára, Ìwọ! Olúwa.
Tänk icke på min ungdoms synder och på mina överträdelser, utan tänk på mig efter din nåd, för din godhets skull, HERRE.
8 Rere àti ẹni ìdúró ṣinṣin ní Olúwa: nítorí náà, ó kọ́ àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ ni ọ̀nà náà.
HERREN är god och rättfärdig, därför undervisar han syndare om vägen.
9 Ó ṣe amọ̀nà àwọn onírẹ̀lẹ̀ ni ohun tí ó dára, ó sì kọ́ àwọn onírẹ̀lẹ̀ ní ọ̀nà rẹ̀.
Han leder de ödmjuka rätt, han lär de ödmjuka sin väg.
10 Gbogbo ipa ọ̀nà Olúwa ni ìfẹ́ àti òdodo tí ó dúró ṣinṣin, fún àwọn tí ó pa májẹ̀mú àti ẹ̀rí rẹ̀ mọ́.
Alla HERRENS vägar äro nåd och trofasthet för dem som hålla hans förbund och vittnesbörd.
11 Nítorí orúkọ rẹ, Olúwa, dárí ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ mi jì mí, nítorí tí ó tóbi.
För ditt namns skull, HERRE, förlåt min missgärning, ty den är stor.
12 Àwọn wo ni ó bẹ̀rù Olúwa? Yóò kọ́ wọn ní ọ̀nà èyí tí wọn yóò yàn.
Finnes det en man som fruktar HERREN, då undervisar han honom om den väg han bör välja.
13 Wọn yóò lo ọjọ́ wọn nínú àlàáfíà, àwọn ọmọ wọn yóò sì gba ilẹ̀ náà.
Han själv skall leva i lycka, och hans efterkommande skola besitta landet.
14 Olúwa fi ọkàn tán, àwọn tí o bẹ̀rù u rẹ̀; ó sọ májẹ̀mú rẹ̀ di mí mọ̀ fún wọn.
HERREN har sin umgängelse med dem som frukta honom, och sitt förbund vill han kungöra för dem.
15 Ojú mi gbé sókè sọ́dọ̀ Olúwa, nítorí pé yóò yọ ẹsẹ̀ mi kúrò nínú àwọ̀n náà.
Mina ögon se alltid till HERREN, ty han drager mina fötter ur nätet.
16 Yípadà sí mi, kí o sì ṣe oore fún mi; nítorí pé mo nìkan wà, mo sì di olùpọ́njú.
Vänd dig till mig och var mig nådig; ty jag är ensam och betryckt.
17 Tì mí lẹ́yìn kúrò nínú ìpọ́njú àyà mi; kí o sì fà mí yọ kúrò nínú ìpọ́njú mi.
Mitt hjärtas ångest är stor; för mig ut ur mitt trångmål.
18 Kíyèsi ìjìyà àti wàhálà mi, kí o sì dárí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ mi jì.
Se till mitt lidande och min vedermöda, och förlåt mig alla mina synder.
19 Kíyèsi ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ọ̀tá mi, tí wọn kórìíra mi pẹ̀lú ìwà ìkà wọn.
Se därtill att mina fiender äro så många och hata mig med orätt.
20 Pa ọkàn mi mọ́, kí o sì gbà mí sílẹ̀; má ṣe jẹ́ kí a fi mí sínú ìtìjú, nítorí pé ìwọ ni ibi ìsádi mi.
Bevara min själ och rädda mig; låt mig icke komma på skam, ty jag tager min tillflykt till dig.
21 Jẹ́ kí òtítọ́ inú àti ìdúró ṣinṣin kí ó pa mí mọ́; nítorí pé mo dúró tì ọ́.
Ostrafflighet och redlighet bevare mig, ty jag förbidar dig.
22 Ra Israẹli padà, Ìwọ Ọlọ́run, nínú gbogbo ìṣòro rẹ̀!
Förlossa Israel, o Gud, ur all dess nöd. Alfabetisk psalm; se Poesi i Ordförkl.