< Psalms 25 >

1 Ti Dafidi. Olúwa, ìwọ ni mo gbé ọkàn mi sókè sí.
Un psalm al lui David. La tine, DOAMNE, îmi înalț sufletul.
2 Ọlọ́run, èmi gbẹ́kẹ̀lé ọ; má ṣe jẹ́ kí ojú ó tì mí má ṣe jẹ́ kí àwọn ọ̀tá mi ó yọ̀ mí.
Dumnezeul meu, în tine mă încred: să nu fiu făcut de rușine, să nu triumfe dușmanii mei asupra mea.
3 Ẹni tí ó dúró tì ọ́ ojú kì yóò tì í, àwọn tí ń ṣẹ̀ láìnídìí ni kí ojú kí ó tì.
Da, nu lăsa pe niciunul dintre cei ce te așteaptă să fie făcut de rușine, să fie făcuți de rușine cei ce calcă legea, fără motiv.
4 Fi ọ̀nà rẹ hàn mí, Olúwa, kọ mi ní ipa tìrẹ;
Arată-mi căile tale, DOAMNE; învață-mă cărările tale.
5 ṣe amọ̀nà mi nínú òtítọ́ ọ̀ rẹ, kí o sì kọ́ mi, nítorí ìwọ ni Ọlọ́run ìgbàlà mi; ìwọ ni mo dúró tì ní gbogbo ọjọ́.
Condu-mă în adevărul tău și învață-mă, căci tu ești Dumnezeul salvării mele; pe tine te aștept toată ziua.
6 Rántí, Olúwa àánú àti ìfẹ́ ẹ̀ rẹ̀ ńlá, torí pé wọ́n ti wà ní ìgbà àtijọ́.
Amintește-ți, DOAMNE, îndurările tale blânde și bunătatea ta iubitoare, pentru că ele au fost din totdeauna.
7 Má ṣe rántí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ ìgbà èwe mi tàbí ìrékọjá mi; gẹ́gẹ́ bí i ìfẹ́ ẹ rẹ̀ rántí mi nítorí tí ìwọ dára, Ìwọ! Olúwa.
Nu îți aminti păcatele tinereții mele, nici fărădelegile mele: amintește-ți de mine conform milei tale, datorită bunătății tale, DOAMNE.
8 Rere àti ẹni ìdúró ṣinṣin ní Olúwa: nítorí náà, ó kọ́ àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ ni ọ̀nà náà.
Bun și integru este DOMNUL; de aceea îi va învăța pe păcătoși pe cale.
9 Ó ṣe amọ̀nà àwọn onírẹ̀lẹ̀ ni ohun tí ó dára, ó sì kọ́ àwọn onírẹ̀lẹ̀ ní ọ̀nà rẹ̀.
Pe cei umili îi va conduce în judecată; și pe cei umili îi va învăța calea sa.
10 Gbogbo ipa ọ̀nà Olúwa ni ìfẹ́ àti òdodo tí ó dúró ṣinṣin, fún àwọn tí ó pa májẹ̀mú àti ẹ̀rí rẹ̀ mọ́.
Toate cărările DOMNULUI sunt milă și adevăr pentru cei ce țin legământul său și mărturiile sale.
11 Nítorí orúkọ rẹ, Olúwa, dárí ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ mi jì mí, nítorí tí ó tóbi.
Datorită numelui tău, DOAMNE, iartă nelegiuirea mea, fiindcă ea este mare.
12 Àwọn wo ni ó bẹ̀rù Olúwa? Yóò kọ́ wọn ní ọ̀nà èyí tí wọn yóò yàn.
Cine este omul care se teme de DOMNUL? Pe el îl va învăța calea pe care să o aleagă.
13 Wọn yóò lo ọjọ́ wọn nínú àlàáfíà, àwọn ọmọ wọn yóò sì gba ilẹ̀ náà.
Sufletul lui va locui în tihnă; și sămânța lui va moșteni pământul.
14 Olúwa fi ọkàn tán, àwọn tí o bẹ̀rù u rẹ̀; ó sọ májẹ̀mú rẹ̀ di mí mọ̀ fún wọn.
Taina DOMNULUI este cu cei ce se tem de el; și le va arăta legământul său.
15 Ojú mi gbé sókè sọ́dọ̀ Olúwa, nítorí pé yóò yọ ẹsẹ̀ mi kúrò nínú àwọ̀n náà.
Ochii mei sunt întotdeauna către DOMNUL, fiindcă îmi va smulge picioarele din ochiurile plasei.
16 Yípadà sí mi, kí o sì ṣe oore fún mi; nítorí pé mo nìkan wà, mo sì di olùpọ́njú.
Întoarce-te spre mine și ai milă de mine, fiindcă sunt pustiit și nenorocit.
17 Tì mí lẹ́yìn kúrò nínú ìpọ́njú àyà mi; kí o sì fà mí yọ kúrò nínú ìpọ́njú mi.
Tulburările inimii mele sunt mărite; scoate-mă din strâmtorările mele.
18 Kíyèsi ìjìyà àti wàhálà mi, kí o sì dárí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ mi jì.
Privește la nenorocirea mea și la durerea mea și iartă toate păcatele mele.
19 Kíyèsi ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ọ̀tá mi, tí wọn kórìíra mi pẹ̀lú ìwà ìkà wọn.
Privește la dușmanii mei, fiindcă sunt mulți și mă urăsc cu ură crudă.
20 Pa ọkàn mi mọ́, kí o sì gbà mí sílẹ̀; má ṣe jẹ́ kí a fi mí sínú ìtìjú, nítorí pé ìwọ ni ibi ìsádi mi.
Păstrează-mi sufletul și eliberează-mă, să nu fiu făcut de rușine, fiindcă în tine mă încred.
21 Jẹ́ kí òtítọ́ inú àti ìdúró ṣinṣin kí ó pa mí mọ́; nítorí pé mo dúró tì ọ́.
Fie ca integritatea și cinstea să mă păstreze, pentru că eu te aștept.
22 Ra Israẹli padà, Ìwọ Ọlọ́run, nínú gbogbo ìṣòro rẹ̀!
Răscumpără pe Israel, Dumnezeule, din toate tulburările lui.

< Psalms 25 >