< Psalms 25 >
1 Ti Dafidi. Olúwa, ìwọ ni mo gbé ọkàn mi sókè sí.
Dávidtól. Hozzád, Örökkévaló, viszem lelkemet.
2 Ọlọ́run, èmi gbẹ́kẹ̀lé ọ; má ṣe jẹ́ kí ojú ó tì mí má ṣe jẹ́ kí àwọn ọ̀tá mi ó yọ̀ mí.
Istenem, tebenned bízom, ne hagyj megszégyenülnöm, ne újjongjanak ellenségeim rajtam!
3 Ẹni tí ó dúró tì ọ́ ojú kì yóò tì í, àwọn tí ń ṣẹ̀ láìnídìí ni kí ojú kí ó tì.
Nem is szégy enülnek meg a téged remélők mind; megszégyenülnek a léhán hűtelenkedők.
4 Fi ọ̀nà rẹ hàn mí, Olúwa, kọ mi ní ipa tìrẹ;
Útjaidat, oh Örökkévaló, tudasd velem, ösvényeidre taníts engem;
5 ṣe amọ̀nà mi nínú òtítọ́ ọ̀ rẹ, kí o sì kọ́ mi, nítorí ìwọ ni Ọlọ́run ìgbàlà mi; ìwọ ni mo dúró tì ní gbogbo ọjọ́.
járass igazságodban és taníts engem, mert te vagy üdvösségem Istene, téged reméllek egész nap.
6 Rántí, Olúwa àánú àti ìfẹ́ ẹ̀ rẹ̀ ńlá, torí pé wọ́n ti wà ní ìgbà àtijọ́.
Emlékezzél meg irgalmadról, oh Örökkévaló, és kegyelmeidről, mert öröktől fogva valók.
7 Má ṣe rántí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ ìgbà èwe mi tàbí ìrékọjá mi; gẹ́gẹ́ bí i ìfẹ́ ẹ rẹ̀ rántí mi nítorí tí ìwọ dára, Ìwọ! Olúwa.
Ifjúhorom vétkeire és bűntetteimre ne emlékezzél; kegyelmed szerint emlékezzél te rólam jóságod kedvéért, oh Örökkévaló!
8 Rere àti ẹni ìdúró ṣinṣin ní Olúwa: nítorí náà, ó kọ́ àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ ni ọ̀nà náà.
Jóságos és egyenes az Örökkévaló, azért útba igazítja a vétkeseket.
9 Ó ṣe amọ̀nà àwọn onírẹ̀lẹ̀ ni ohun tí ó dára, ó sì kọ́ àwọn onírẹ̀lẹ̀ ní ọ̀nà rẹ̀.
Járatja az alázatosakat a jog szerint és tanűja az alázatosokat az ő útjára.
10 Gbogbo ipa ọ̀nà Olúwa ni ìfẹ́ àti òdodo tí ó dúró ṣinṣin, fún àwọn tí ó pa májẹ̀mú àti ẹ̀rí rẹ̀ mọ́.
Mind az Őrökkévalónak ösvényei szeretet és igazság azoknak, kik megtartják szövetségét és bízonysága. it.
11 Nítorí orúkọ rẹ, Olúwa, dárí ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ mi jì mí, nítorí tí ó tóbi.
Neved kedvéért, oh Örökkévaló, bocsásd meg bűnömet, mert nagy az.
12 Àwọn wo ni ó bẹ̀rù Olúwa? Yóò kọ́ wọn ní ọ̀nà èyí tí wọn yóò yàn.
Ki az a férfi, a ki istenfélő? Azt igazítja azon útra, melyet válaszszon.
13 Wọn yóò lo ọjọ́ wọn nínú àlàáfíà, àwọn ọmọ wọn yóò sì gba ilẹ̀ náà.
Lelke jólétben marad és magzatja bírni fogja az országot.
14 Olúwa fi ọkàn tán, àwọn tí o bẹ̀rù u rẹ̀; ó sọ májẹ̀mú rẹ̀ di mí mọ̀ fún wọn.
Az Örökkévaló titka az ő tisztelőinél van, és szövetségét tudatja velük.
15 Ojú mi gbé sókè sọ́dọ̀ Olúwa, nítorí pé yóò yọ ẹsẹ̀ mi kúrò nínú àwọ̀n náà.
Szemeim mindig az Örökkévalóra néznek, mert ő húzza ki a hálóból lábaimat.
16 Yípadà sí mi, kí o sì ṣe oore fún mi; nítorí pé mo nìkan wà, mo sì di olùpọ́njú.
Fordulj hozzám és kegyelmezz nekem, mert magános és szegény vagyok.
17 Tì mí lẹ́yìn kúrò nínú ìpọ́njú àyà mi; kí o sì fà mí yọ kúrò nínú ìpọ́njú mi.
Szívem szorongásai vajha tágulnának, szorúltságaimból vezess ki engem!
18 Kíyèsi ìjìyà àti wàhálà mi, kí o sì dárí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ mi jì.
Lásd nyomorúságomat és szenvedésemet és bocsásd meg mind a vétkeimet.
19 Kíyèsi ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ọ̀tá mi, tí wọn kórìíra mi pẹ̀lú ìwà ìkà wọn.
Lásd ellenségeimet, hogy sokan vannak, és erőszakot tevő gyűlölettel gyűlölnek engem.
20 Pa ọkàn mi mọ́, kí o sì gbà mí sílẹ̀; má ṣe jẹ́ kí a fi mí sínú ìtìjú, nítorí pé ìwọ ni ibi ìsádi mi.
Őrizd meg lelkemet és ments meg engem, ne szégyenüljek meg, mert benned van menedékem.
21 Jẹ́ kí òtítọ́ inú àti ìdúró ṣinṣin kí ó pa mí mọ́; nítorí pé mo dúró tì ọ́.
Gáncstalanság és egyenesség óvjanak meg engem, mert téged reméllek.
22 Ra Israẹli padà, Ìwọ Ọlọ́run, nínú gbogbo ìṣòro rẹ̀!
Váltsd meg, Isten, Izraélt mind a szorongásaiból!