< Psalms 25 >

1 Ti Dafidi. Olúwa, ìwọ ni mo gbé ọkàn mi sókè sí.
E IEHOVA, ke hapai nei au i ko'u uhane ia oe.
2 Ọlọ́run, èmi gbẹ́kẹ̀lé ọ; má ṣe jẹ́ kí ojú ó tì mí má ṣe jẹ́ kí àwọn ọ̀tá mi ó yọ̀ mí.
E kuu Akua, maluna ou e hilinai aku nei au; Aole au e hoka; Mai noho a lanakila mai ko'u poe enemi maluna o'u.
3 Ẹni tí ó dúró tì ọ́ ojú kì yóò tì í, àwọn tí ń ṣẹ̀ láìnídìí ni kí ojú kí ó tì.
Oia hoi, e hoka ole ka poe manaolana ia oe; E hoka no nae ka poe lawehala wale.
4 Fi ọ̀nà rẹ hàn mí, Olúwa, kọ mi ní ipa tìrẹ;
E hoike mai, e Iehova, i kou mau alanui ia'u: E ao mai oe ia'u i kou mau kuamoo.
5 ṣe amọ̀nà mi nínú òtítọ́ ọ̀ rẹ, kí o sì kọ́ mi, nítorí ìwọ ni Ọlọ́run ìgbàlà mi; ìwọ ni mo dúró tì ní gbogbo ọjọ́.
E alakai oe ia'u ma kau olelo oiaio, E ao mai hoi oe ia'u; No ka mea, o oe no ko'u Akua e ola'i: He manaolana ko'u ia oe a po ka la.
6 Rántí, Olúwa àánú àti ìfẹ́ ẹ̀ rẹ̀ ńlá, torí pé wọ́n ti wà ní ìgbà àtijọ́.
E hoomanao oe, e Iehova, i kou aloha a me kou lokomaikai; No ka mea, he mau mea kahiko loa mai no ia.
7 Má ṣe rántí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ ìgbà èwe mi tàbí ìrékọjá mi; gẹ́gẹ́ bí i ìfẹ́ ẹ rẹ̀ rántí mi nítorí tí ìwọ dára, Ìwọ! Olúwa.
Mai manao mai oe i na hewa o ko'u wa opiopio, me na hala o'u. E hoomanao mai oe ia'u e like me kou aloha, no kou lokomaikai
8 Rere àti ẹni ìdúró ṣinṣin ní Olúwa: nítorí náà, ó kọ́ àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ ni ọ̀nà náà.
He maikai a he pololei no ko Iehova; Nolaila ia e ao mai ai i ka poe lawehala i kona alanui.
9 Ó ṣe amọ̀nà àwọn onírẹ̀lẹ̀ ni ohun tí ó dára, ó sì kọ́ àwọn onírẹ̀lẹ̀ ní ọ̀nà rẹ̀.
E alakai oia i ka poe akahai ma ka pono: E ao mai no hoi oia i ka poe hoohaahaa i kona aoao.
10 Gbogbo ipa ọ̀nà Olúwa ni ìfẹ́ àti òdodo tí ó dúró ṣinṣin, fún àwọn tí ó pa májẹ̀mú àti ẹ̀rí rẹ̀ mọ́.
O na aoao a pau o Iehova he aloha no ia me ka oiaio, I ka poe i malama i kona berita a me kana mau kauoha.
11 Nítorí orúkọ rẹ, Olúwa, dárí ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ mi jì mí, nítorí tí ó tóbi.
No kou inoa, e Iehova, e kala mai ai oe i ko'u hewa; No ka mea, he nui no ia.
12 Àwọn wo ni ó bẹ̀rù Olúwa? Yóò kọ́ wọn ní ọ̀nà èyí tí wọn yóò yàn.
Owai la ke kanaka i weliweli aku ia Iehova? Oia kana e ao mai ai i ka aoao ana e koho ai.
13 Wọn yóò lo ọjọ́ wọn nínú àlàáfíà, àwọn ọmọ wọn yóò sì gba ilẹ̀ náà.
E noho kona uhane ma ka maikai. E ili hoi ka honua i kana mau keiki.
14 Olúwa fi ọkàn tán, àwọn tí o bẹ̀rù u rẹ̀; ó sọ májẹ̀mú rẹ̀ di mí mọ̀ fún wọn.
O ka manao paa o Iehova aia no ia me ka poe weliweli ia ia: E hoike mai no hoi oia i kona berita ia lakou.
15 Ojú mi gbé sókè sọ́dọ̀ Olúwa, nítorí pé yóò yọ ẹsẹ̀ mi kúrò nínú àwọ̀n náà.
E kau mau ana ko'u mau maka ia Iehova; No ka mea, e kaili ae oia i ko'u mau wawae mailoko ae o ka upena.
16 Yípadà sí mi, kí o sì ṣe oore fún mi; nítorí pé mo nìkan wà, mo sì di olùpọ́njú.
E maliu mai oe ia'u a e aloha mai ia'u. No ka mea, ua mehameha au a ua popilikia.
17 Tì mí lẹ́yìn kúrò nínú ìpọ́njú àyà mi; kí o sì fà mí yọ kúrò nínú ìpọ́njú mi.
Ua nui ae nei ka ehaeha o ko'u naau: E lawe ae oe ia'u mailoko ae o ko'u popilikia.
18 Kíyèsi ìjìyà àti wàhálà mi, kí o sì dárí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ mi jì.
E nana mai i ko'u pilikia a me ko'u eha; A e kala mai i ko'u hewa a pau.
19 Kíyèsi ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ọ̀tá mi, tí wọn kórìíra mi pẹ̀lú ìwà ìkà wọn.
E manao mai oe i kuu mau enemi, No ka mea, he nui no lakou; A ua inaina mai lakou ia'u me ka huhu awahia.
20 Pa ọkàn mi mọ́, kí o sì gbà mí sílẹ̀; má ṣe jẹ́ kí a fi mí sínú ìtìjú, nítorí pé ìwọ ni ibi ìsádi mi.
E malama mai oe i kuu uhane, a e hoola mai ia'u; E hoka ole au, no ka mea, e hilinai aku au ia oe.
21 Jẹ́ kí òtítọ́ inú àti ìdúró ṣinṣin kí ó pa mí mọ́; nítorí pé mo dúró tì ọ́.
E hoomalu ka pono me ka pololei ia'u, No ka mea, ke manao laua aku nei au ia oe.
22 Ra Israẹli padà, Ìwọ Ọlọ́run, nínú gbogbo ìṣòro rẹ̀!
E hoola ae oe, e ke Akua, ia Iseraela, Mai loko ae o kona mau popilikia a pau.

< Psalms 25 >