< Psalms 25 >

1 Ti Dafidi. Olúwa, ìwọ ni mo gbé ọkàn mi sókè sí.
Thaburi ya Daudi Wee Jehova, ngoro yakwa ndĩmĩroretie na igũrũ kũrĩ we;
2 Ọlọ́run, èmi gbẹ́kẹ̀lé ọ; má ṣe jẹ́ kí ojú ó tì mí má ṣe jẹ́ kí àwọn ọ̀tá mi ó yọ̀ mí.
Wee Ngai wakwa, nowe ndĩhokete. Ndũkareke njonorithio, o na kana ũreke thũ ciakwa ingenerere.
3 Ẹni tí ó dúró tì ọ́ ojú kì yóò tì í, àwọn tí ń ṣẹ̀ láìnídìí ni kí ojú kí ó tì.
Gũtirĩ mũndũ ũkwĩhokete ũgaaconorithio o na rĩ, no arĩa mekaga andũ ũũru hatarĩ gĩtũmi-rĩ, acio nĩo magaconorithio.
4 Fi ọ̀nà rẹ hàn mí, Olúwa, kọ mi ní ipa tìrẹ;
Wee Jehova, nyonia mĩthiĩre yaku, ũũmenyithie njĩra ciaku;
5 ṣe amọ̀nà mi nínú òtítọ́ ọ̀ rẹ, kí o sì kọ́ mi, nítorí ìwọ ni Ọlọ́run ìgbàlà mi; ìwọ ni mo dúró tì ní gbogbo ọjọ́.
ndongoria ũhoro-inĩ waku wa ma na ũndutage, nĩgũkorwo nĩwe Ngai ũrĩa ũũhonokagia, na nĩwe kĩĩrĩgĩrĩro gĩakwa mũthenya wothe.
6 Rántí, Olúwa àánú àti ìfẹ́ ẹ̀ rẹ̀ ńlá, torí pé wọ́n ti wà ní ìgbà àtijọ́.
Jehova, ririkana tha ciaku nyingĩ o na wendo waku, nĩgũkorwo nĩ cia kuuma o tene.
7 Má ṣe rántí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ ìgbà èwe mi tàbí ìrékọjá mi; gẹ́gẹ́ bí i ìfẹ́ ẹ rẹ̀ rántí mi nítorí tí ìwọ dára, Ìwọ! Olúwa.
Ndũkaririkane mehia ma ũnini wakwa, o na kana mehia makwa ma ũremi; ndirikana kũringana na wendani waku, nĩ ũndũ wa wega waku, Wee Jehova.
8 Rere àti ẹni ìdúró ṣinṣin ní Olúwa: nítorí náà, ó kọ́ àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ ni ọ̀nà náà.
Jehova nĩ mwega na nĩ mũrũngĩrĩru; nĩ ũndũ ũcio andũ arĩa ehia nĩarĩmonagĩrĩria njĩra ciake.
9 Ó ṣe amọ̀nà àwọn onírẹ̀lẹ̀ ni ohun tí ó dára, ó sì kọ́ àwọn onírẹ̀lẹ̀ ní ọ̀nà rẹ̀.
Atongoragia andũ arĩa menyiihagia na njĩra ĩrĩa yagĩrĩire, na akamarutaga njĩra yake.
10 Gbogbo ipa ọ̀nà Olúwa ni ìfẹ́ àti òdodo tí ó dúró ṣinṣin, fún àwọn tí ó pa májẹ̀mú àti ẹ̀rí rẹ̀ mọ́.
Njĩra ciothe cia Jehova nĩ cia wendani na wĩhokeku, harĩ arĩa mamenyagĩrĩra kĩrĩkanĩro gĩake.
11 Nítorí orúkọ rẹ, Olúwa, dárí ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ mi jì mí, nítorí tí ó tóbi.
Wee Jehova, nĩ ũndũ wa rĩĩtwa rĩaku-rĩ, ndekera mehia makwa, o na gũtuĩka nĩ manene.
12 Àwọn wo ni ó bẹ̀rù Olúwa? Yóò kọ́ wọn ní ọ̀nà èyí tí wọn yóò yàn.
Mũndũ ũrĩa mwĩtigĩri Jehova nũũ? Mũndũ ũcio nĩarĩmuonagĩrĩria njĩra ĩrĩa aagĩrĩirwo nĩ kũgera.
13 Wọn yóò lo ọjọ́ wọn nínú àlàáfíà, àwọn ọmọ wọn yóò sì gba ilẹ̀ náà.
Mũndũ ũcio egũtũũra matukũ make agaacĩire, nacio njiaro ciake nĩikaagaya bũrũri.
14 Olúwa fi ọkàn tán, àwọn tí o bẹ̀rù u rẹ̀; ó sọ májẹ̀mú rẹ̀ di mí mọ̀ fún wọn.
Jehova nĩehokaga andũ arĩa mamwĩtigagĩra; nĩo amenyithagia kĩrĩkanĩro gĩake.
15 Ojú mi gbé sókè sọ́dọ̀ Olúwa, nítorí pé yóò yọ ẹsẹ̀ mi kúrò nínú àwọ̀n náà.
Maitho makwa maikaraga hĩndĩ ciothe macũthĩrĩirie Jehova, nĩgũkorwo nowe wiki ũngĩteithũkithia magũrũ makwa mũtego-inĩ.
16 Yípadà sí mi, kí o sì ṣe oore fún mi; nítorí pé mo nìkan wà, mo sì di olùpọ́njú.
Hũgũkĩra, ũnyonie ũtugi waku, nĩgũkorwo ndĩ o nyiki na ndĩ mũnyamarĩku.
17 Tì mí lẹ́yìn kúrò nínú ìpọ́njú àyà mi; kí o sì fà mí yọ kúrò nínú ìpọ́njú mi.
Mathĩĩna ma ngoro yakwa nĩmaingĩhĩte; niinĩra ruo rũrĩa ndĩ naruo.
18 Kíyèsi ìjìyà àti wàhálà mi, kí o sì dárí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ mi jì.
Rora mĩnyamaro yakwa o na gũtangĩka gwakwa, ũkĩndekere mehia makwa mothe.
19 Kíyèsi ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ọ̀tá mi, tí wọn kórìíra mi pẹ̀lú ìwà ìkà wọn.
Rora thũ ciakwa wone ũrĩa cingĩhĩte, nacio iithũire na rũthũũro rũtarĩ tha!
20 Pa ọkàn mi mọ́, kí o sì gbà mí sílẹ̀; má ṣe jẹ́ kí a fi mí sínú ìtìjú, nítorí pé ìwọ ni ibi ìsádi mi.
Menyagĩrĩra muoyo wakwa na ũũthare; ndũkareke njonorithio, nĩgũkorwo nĩ harĩwe njũragĩra.
21 Jẹ́ kí òtítọ́ inú àti ìdúró ṣinṣin kí ó pa mí mọ́; nítorí pé mo dúró tì ọ́.
Wĩkindĩru wa ngoro na ũrũngĩrĩru irongitagĩra, tondũ nĩwe njĩrĩgagĩrĩra.
22 Ra Israẹli padà, Ìwọ Ọlọ́run, nínú gbogbo ìṣòro rẹ̀!
Wee Ngai, gĩkũũre andũ a Isiraeli, moime mathĩĩna-inĩ mao mothe!

< Psalms 25 >