< Psalms 25 >

1 Ti Dafidi. Olúwa, ìwọ ni mo gbé ọkàn mi sókè sí.
Par David. Vers toi, Yahvé, j'élève mon âme.
2 Ọlọ́run, èmi gbẹ́kẹ̀lé ọ; má ṣe jẹ́ kí ojú ó tì mí má ṣe jẹ́ kí àwọn ọ̀tá mi ó yọ̀ mí.
Mon Dieu, je me suis confié à toi. Ne me laisse pas avoir honte. Ne laisse pas mes ennemis triompher de moi.
3 Ẹni tí ó dúró tì ọ́ ojú kì yóò tì í, àwọn tí ń ṣẹ̀ láìnídìí ni kí ojú kí ó tì.
Oui, celui qui t'attend n'aura pas à rougir. Ceux qui trahissent sans raison seront honteux.
4 Fi ọ̀nà rẹ hàn mí, Olúwa, kọ mi ní ipa tìrẹ;
Montre-moi tes voies, Yahvé. Apprenez-moi vos chemins.
5 ṣe amọ̀nà mi nínú òtítọ́ ọ̀ rẹ, kí o sì kọ́ mi, nítorí ìwọ ni Ọlọ́run ìgbàlà mi; ìwọ ni mo dúró tì ní gbogbo ọjọ́.
Guide-moi dans ta vérité, et enseigne-moi, car tu es le Dieu de mon salut. Je t'attends toute la journée.
6 Rántí, Olúwa àánú àti ìfẹ́ ẹ̀ rẹ̀ ńlá, torí pé wọ́n ti wà ní ìgbà àtijọ́.
Yahvé, souviens-toi de ta tendresse et de ta bonté, car ils sont d'un autre temps.
7 Má ṣe rántí àwọn ẹ̀ṣẹ̀ ìgbà èwe mi tàbí ìrékọjá mi; gẹ́gẹ́ bí i ìfẹ́ ẹ rẹ̀ rántí mi nítorí tí ìwọ dára, Ìwọ! Olúwa.
Ne te souviens pas des péchés de ma jeunesse, ni de mes transgressions. Souviens-toi de moi selon ta bonté, pour l'amour de ta bonté, Yahvé.
8 Rere àti ẹni ìdúró ṣinṣin ní Olúwa: nítorí náà, ó kọ́ àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ ni ọ̀nà náà.
Yahvé est bon et droit, c'est pourquoi il instruira les pécheurs dans la voie.
9 Ó ṣe amọ̀nà àwọn onírẹ̀lẹ̀ ni ohun tí ó dára, ó sì kọ́ àwọn onírẹ̀lẹ̀ ní ọ̀nà rẹ̀.
Il guidera les humbles dans la justice. Il enseignera sa voie aux humbles.
10 Gbogbo ipa ọ̀nà Olúwa ni ìfẹ́ àti òdodo tí ó dúró ṣinṣin, fún àwọn tí ó pa májẹ̀mú àti ẹ̀rí rẹ̀ mọ́.
Tous les chemins de l'Éternel sont la bonté et la vérité. à ceux qui gardent son alliance et ses témoignages.
11 Nítorí orúkọ rẹ, Olúwa, dárí ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ mi jì mí, nítorí tí ó tóbi.
A cause de ton nom, Yahvé, pardonnez mon iniquité, car elle est grande.
12 Àwọn wo ni ó bẹ̀rù Olúwa? Yóò kọ́ wọn ní ọ̀nà èyí tí wọn yóò yàn.
Quel est l'homme qui craint Yahvé? Il l'instruira dans la voie qu'il choisira.
13 Wọn yóò lo ọjọ́ wọn nínú àlàáfíà, àwọn ọmọ wọn yóò sì gba ilẹ̀ náà.
Son âme reposera en paix. Sa progéniture héritera de la terre.
14 Olúwa fi ọkàn tán, àwọn tí o bẹ̀rù u rẹ̀; ó sọ májẹ̀mú rẹ̀ di mí mọ̀ fún wọn.
L'amitié de Yahvé est avec ceux qui le craignent. Il leur montrera son alliance.
15 Ojú mi gbé sókè sọ́dọ̀ Olúwa, nítorí pé yóò yọ ẹsẹ̀ mi kúrò nínú àwọ̀n náà.
Mes yeux sont toujours fixés sur Yahvé, car il arrachera mes pieds du filet.
16 Yípadà sí mi, kí o sì ṣe oore fún mi; nítorí pé mo nìkan wà, mo sì di olùpọ́njú.
Tournez-vous vers moi, et ayez pitié de moi, car je suis désolée et affligée.
17 Tì mí lẹ́yìn kúrò nínú ìpọ́njú àyà mi; kí o sì fà mí yọ kúrò nínú ìpọ́njú mi.
Les troubles de mon cœur s'élargissent. Oh, sors-moi de ma détresse.
18 Kíyèsi ìjìyà àti wàhálà mi, kí o sì dárí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ mi jì.
Considérez mon affliction et mon travail. Pardonnez tous mes péchés.
19 Kíyèsi ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ọ̀tá mi, tí wọn kórìíra mi pẹ̀lú ìwà ìkà wọn.
Considérez mes ennemis, car ils sont nombreux. Ils me haïssent d'une haine cruelle.
20 Pa ọkàn mi mọ́, kí o sì gbà mí sílẹ̀; má ṣe jẹ́ kí a fi mí sínú ìtìjú, nítorí pé ìwọ ni ibi ìsádi mi.
Oh, garde mon âme, et délivre-moi. Que je ne sois pas déçu, car je me réfugie en toi.
21 Jẹ́ kí òtítọ́ inú àti ìdúró ṣinṣin kí ó pa mí mọ́; nítorí pé mo dúró tì ọ́.
Que l'intégrité et la droiture me préservent, car je t'attends.
22 Ra Israẹli padà, Ìwọ Ọlọ́run, nínú gbogbo ìṣòro rẹ̀!
Dieu, rachète Israël de tous ses problèmes.

< Psalms 25 >