< Psalms 24 >

1 Ti Dafidi. Saamu. Ti Olúwa ni ilẹ̀, àti ẹ̀kún rẹ̀, ayé àti àwọn tí ó tẹ̀dó sínú rẹ̀;
Un psalm al lui David. AL DOMNULUI este pământul și plinătatea lui, lumea și cei ce locuiesc în ea.
2 nítorí ó fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ lélẹ̀ lórí òkun ó sì gbé e kalẹ̀ lórí àwọn ìṣàn omi.
Fiindcă l-a fondat peste mări și l-a întemeiat peste potopuri.
3 Ta ni yóò gun orí òkè Olúwa lọ? Ta ni yóò dúró ní ibi mímọ́ rẹ̀?
Cine va urca la muntele DOMNULUI? Sau cine se va ridica la locul său sfânt?
4 Ẹni tí ó ní ọwọ́ mímọ́ àti àyà funfun, ẹni tí kò gbé ọkàn rẹ̀ sókè sí asán tí kò sì búra èké.
Cel ce are mâini nevinovate și o inimă pură; cel ce nu și-a înălțat sufletul spre deșertăciune, nici nu a jurat înșelător.
5 Òun ni yóò rí ìbùkún gbà láti ọ̀dọ̀ Olúwa, àti òdodo lọ́wọ́ Ọlọ́run ìgbàlà rẹ̀.
El va primi binecuvântare de la DOMNUL și dreptate de la Dumnezeul salvării sale.
6 Èyí ni ìran àwọn tí ń ṣe àfẹ́rí rẹ̀, tí ń ṣe àfẹ́rí rẹ̀, Ọlọ́run Jakọbu. (Sela)
Aceasta este generația celor care îl caută, care caută fața ta, Iacob. (Selah)
7 Ẹ gbé orí yín sókè, háà! Ẹ̀yin ọ̀nà; kí á sì gbe yín sókè, ẹyin ìlẹ̀kùn ayérayé! Kí ọba ògo le è wọlé.
Înălțați-vă capetele voastre, porților; și fiți înălțate, voi uși veșnice; și Împăratul gloriei va intra.
8 Ta ni ọba ògo náà? Olúwa tí ó lágbára tí ó sì le, Olúwa gan an, tí ó lágbára ní ogun.
Cine este acest Împărat al gloriei? DOMNUL puternic și tare, DOMNUL tare în bătălie.
9 Gbé orí yín sókè, ẹyin ọ̀nà; kí a sì gbé e yín sókè, ẹ̀yin ìlẹ̀kùn ayérayé, kí Ọba ògo le è wọlé wá.
Înălțați-vă capetele voastre, porților; înălțați-le, voi uși veșnice; și Împăratul gloriei va intra.
10 Ta ni Ọba ògo náà? Olúwa àwọn ọmọ-ogun Òun ni Ọba ògo náà. (Sela)
Cine este acest Împărat al gloriei? DOMNUL oștirilor, el este Împăratul gloriei. (Selah)

< Psalms 24 >