< Psalms 24 >
1 Ti Dafidi. Saamu. Ti Olúwa ni ilẹ̀, àti ẹ̀kún rẹ̀, ayé àti àwọn tí ó tẹ̀dó sínú rẹ̀;
Av David; en salme. Jorden hører Herren til - og alt det som fyller den, jorderike og de som bor der.
2 nítorí ó fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ lélẹ̀ lórí òkun ó sì gbé e kalẹ̀ lórí àwọn ìṣàn omi.
For han har grunnlagt den på hav og stilt den fast på strømmer.
3 Ta ni yóò gun orí òkè Olúwa lọ? Ta ni yóò dúró ní ibi mímọ́ rẹ̀?
Hvem skal stige op på Herrens berg, og hvem skal stå på hans hellige sted?
4 Ẹni tí ó ní ọwọ́ mímọ́ àti àyà funfun, ẹni tí kò gbé ọkàn rẹ̀ sókè sí asán tí kò sì búra èké.
Den som har uskyldige hender og et rent hjerte, som ikke har vendt sin hu til løgn og ikke har svoret falskelig.
5 Òun ni yóò rí ìbùkún gbà láti ọ̀dọ̀ Olúwa, àti òdodo lọ́wọ́ Ọlọ́run ìgbàlà rẹ̀.
Han skal motta velsignelse fra Herren og rettferdighet fra sin frelses Gud.
6 Èyí ni ìran àwọn tí ń ṣe àfẹ́rí rẹ̀, tí ń ṣe àfẹ́rí rẹ̀, Ọlọ́run Jakọbu. (Sela)
Dette er deres ætt som spør efter ham, de som søker ditt åsyn, Jakobs barn. (Sela)
7 Ẹ gbé orí yín sókè, háà! Ẹ̀yin ọ̀nà; kí á sì gbe yín sókè, ẹyin ìlẹ̀kùn ayérayé! Kí ọba ògo le è wọlé.
Løft, I porter, eders hoder, og løft eder, I evige dører, så herlighetens konge kan dra inn!
8 Ta ni ọba ògo náà? Olúwa tí ó lágbára tí ó sì le, Olúwa gan an, tí ó lágbára ní ogun.
Hvem er den herlighetens konge? Herren, sterk og veldig, Herren veldig i strid.
9 Gbé orí yín sókè, ẹyin ọ̀nà; kí a sì gbé e yín sókè, ẹ̀yin ìlẹ̀kùn ayérayé, kí Ọba ògo le è wọlé wá.
Løft, I porter, eders hoder, og løft eder, I evige dører, så herlighetens konge kan dra inn!
10 Ta ni Ọba ògo náà? Olúwa àwọn ọmọ-ogun Òun ni Ọba ògo náà. (Sela)
Hvem er den herlighetens konge? Herren, hærskarenes Gud, han er herlighetens konge. (Sela)