< Psalms 24 >

1 Ti Dafidi. Saamu. Ti Olúwa ni ilẹ̀, àti ẹ̀kún rẹ̀, ayé àti àwọn tí ó tẹ̀dó sínú rẹ̀;
לדוד מזמור ליהוה הארץ ומלואה תבל וישבי בה׃
2 nítorí ó fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ lélẹ̀ lórí òkun ó sì gbé e kalẹ̀ lórí àwọn ìṣàn omi.
כי הוא על ימים יסדה ועל נהרות יכוננה׃
3 Ta ni yóò gun orí òkè Olúwa lọ? Ta ni yóò dúró ní ibi mímọ́ rẹ̀?
מי יעלה בהר יהוה ומי יקום במקום קדשו׃
4 Ẹni tí ó ní ọwọ́ mímọ́ àti àyà funfun, ẹni tí kò gbé ọkàn rẹ̀ sókè sí asán tí kò sì búra èké.
נקי כפים ובר לבב אשר לא נשא לשוא נפשי ולא נשבע למרמה׃
5 Òun ni yóò rí ìbùkún gbà láti ọ̀dọ̀ Olúwa, àti òdodo lọ́wọ́ Ọlọ́run ìgbàlà rẹ̀.
ישא ברכה מאת יהוה וצדקה מאלהי ישעו׃
6 Èyí ni ìran àwọn tí ń ṣe àfẹ́rí rẹ̀, tí ń ṣe àfẹ́rí rẹ̀, Ọlọ́run Jakọbu. (Sela)
זה דור דרשו מבקשי פניך יעקב סלה׃
7 Ẹ gbé orí yín sókè, háà! Ẹ̀yin ọ̀nà; kí á sì gbe yín sókè, ẹyin ìlẹ̀kùn ayérayé! Kí ọba ògo le è wọlé.
שאו שערים ראשיכם והנשאו פתחי עולם ויבוא מלך הכבוד׃
8 Ta ni ọba ògo náà? Olúwa tí ó lágbára tí ó sì le, Olúwa gan an, tí ó lágbára ní ogun.
מי זה מלך הכבוד יהוה עזוז וגבור יהוה גבור מלחמה׃
9 Gbé orí yín sókè, ẹyin ọ̀nà; kí a sì gbé e yín sókè, ẹ̀yin ìlẹ̀kùn ayérayé, kí Ọba ògo le è wọlé wá.
שאו שערים ראשיכם ושאו פתחי עולם ויבא מלך הכבוד׃
10 Ta ni Ọba ògo náà? Olúwa àwọn ọmọ-ogun Òun ni Ọba ògo náà. (Sela)
מי הוא זה מלך הכבוד יהוה צבאות הוא מלך הכבוד סלה׃

< Psalms 24 >