< Psalms 24 >

1 Ti Dafidi. Saamu. Ti Olúwa ni ilẹ̀, àti ẹ̀kún rẹ̀, ayé àti àwọn tí ó tẹ̀dó sínú rẹ̀;
Psaume de David. La terre appartient à l'Eternel, avec tout ce qui est en elle, la terre habitable, et ceux qui y habitent.
2 nítorí ó fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ lélẹ̀ lórí òkun ó sì gbé e kalẹ̀ lórí àwọn ìṣàn omi.
Car il l'a fondée sur les mers, et l'a posée sur les fleuves.
3 Ta ni yóò gun orí òkè Olúwa lọ? Ta ni yóò dúró ní ibi mímọ́ rẹ̀?
Qui est-ce qui montera en la montagne de l'Eternel? et qui est-ce qui demeurera dans le lieu de sa sainteté?
4 Ẹni tí ó ní ọwọ́ mímọ́ àti àyà funfun, ẹni tí kò gbé ọkàn rẹ̀ sókè sí asán tí kò sì búra èké.
Ce sera l'homme qui a les mains pures et le cœur net, qui n'aspire point de son âme à la fausseté, et qui ne jure point en tromperie.
5 Òun ni yóò rí ìbùkún gbà láti ọ̀dọ̀ Olúwa, àti òdodo lọ́wọ́ Ọlọ́run ìgbàlà rẹ̀.
Il recevra bénédiction de l'Eternel, et justice de Dieu son Sauveur.
6 Èyí ni ìran àwọn tí ń ṣe àfẹ́rí rẹ̀, tí ń ṣe àfẹ́rí rẹ̀, Ọlọ́run Jakọbu. (Sela)
Tels sont ceux qui l'invoquent, ceux qui cherchent ta face en Jacob: (Sélah)
7 Ẹ gbé orí yín sókè, háà! Ẹ̀yin ọ̀nà; kí á sì gbe yín sókè, ẹyin ìlẹ̀kùn ayérayé! Kí ọba ògo le è wọlé.
Portes, élevez vos linteaux, et vous portes éternelles, haussez-vous, et le Roi de gloire entrera.
8 Ta ni ọba ògo náà? Olúwa tí ó lágbára tí ó sì le, Olúwa gan an, tí ó lágbára ní ogun.
Qui est ce Roi de gloire? C'est l'Eternel fort et puissant, l'Eternel puissant en bataille.
9 Gbé orí yín sókè, ẹyin ọ̀nà; kí a sì gbé e yín sókè, ẹ̀yin ìlẹ̀kùn ayérayé, kí Ọba ògo le è wọlé wá.
Portes, élevez vos linteaux, élevez-les aussi, vous portes éternelles, et le Roi de gloire entrera.
10 Ta ni Ọba ògo náà? Olúwa àwọn ọmọ-ogun Òun ni Ọba ògo náà. (Sela)
Qui est ce Roi de gloire? L'Eternel des armées; c'est lui qui est le Roi de gloire: (Sélah)

< Psalms 24 >