< Psalms 24 >

1 Ti Dafidi. Saamu. Ti Olúwa ni ilẹ̀, àti ẹ̀kún rẹ̀, ayé àti àwọn tí ó tẹ̀dó sínú rẹ̀;
David’s. A Melody. To Yahweh, belongeth, The earth and the fulness thereof, The world, and they who dwell therein;
2 nítorí ó fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ lélẹ̀ lórí òkun ó sì gbé e kalẹ̀ lórí àwọn ìṣàn omi.
For, he, upon the seas, hath founded it, and upon the currents, doth make it firm.
3 Ta ni yóò gun orí òkè Olúwa lọ? Ta ni yóò dúró ní ibi mímọ́ rẹ̀?
Who shall ascend the mountain of Yahweh? And who shall stand in his holy place?
4 Ẹni tí ó ní ọwọ́ mímọ́ àti àyà funfun, ẹni tí kò gbé ọkàn rẹ̀ sókè sí asán tí kò sì búra èké.
The clean of hands, and pure of heart, —who hath not uplifted, to falsehood, his soul, nor sworn deceitfully,
5 Òun ni yóò rí ìbùkún gbà láti ọ̀dọ̀ Olúwa, àti òdodo lọ́wọ́ Ọlọ́run ìgbàlà rẹ̀.
Shall bear away a blessing from Yahweh, and righteousness, from his delivering God.
6 Èyí ni ìran àwọn tí ń ṣe àfẹ́rí rẹ̀, tí ń ṣe àfẹ́rí rẹ̀, Ọlọ́run Jakọbu. (Sela)
This, is the generation of them who inquire of him, who seek thy face, O God of Jacob. (Selah)
7 Ẹ gbé orí yín sókè, háà! Ẹ̀yin ọ̀nà; kí á sì gbe yín sókè, ẹyin ìlẹ̀kùn ayérayé! Kí ọba ògo le è wọlé.
Lift up, O ye gates, your heads, and lift yourselves up, ye age-abiding doors, That the king of glory may come in.
8 Ta ni ọba ògo náà? Olúwa tí ó lágbára tí ó sì le, Olúwa gan an, tí ó lágbára ní ogun.
Who is the king of glory? Yahweh, strong and mighty, Yahweh, mighty in war.
9 Gbé orí yín sókè, ẹyin ọ̀nà; kí a sì gbé e yín sókè, ẹ̀yin ìlẹ̀kùn ayérayé, kí Ọba ògo le è wọlé wá.
Lift up, O ye gates, your heads, yea lift [them] up, ye age-abiding doors, That the king of glory may come in.
10 Ta ni Ọba ògo náà? Olúwa àwọn ọmọ-ogun Òun ni Ọba ògo náà. (Sela)
Who then is the king of glory? Yahweh of hosts, He, is the king of glory. (Selah)

< Psalms 24 >