< Psalms 24 >
1 Ti Dafidi. Saamu. Ti Olúwa ni ilẹ̀, àti ẹ̀kún rẹ̀, ayé àti àwọn tí ó tẹ̀dó sínú rẹ̀;
A PSALM OF DAVID. To YHWH [is] the earth and its fullness, The world and the inhabitants in it.
2 nítorí ó fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ lélẹ̀ lórí òkun ó sì gbé e kalẹ̀ lórí àwọn ìṣàn omi.
For He has founded it on the seas, And He establishes it on the floods.
3 Ta ni yóò gun orí òkè Olúwa lọ? Ta ni yóò dúró ní ibi mímọ́ rẹ̀?
Who goes up into the hill of YHWH? And who rises up in His holy place?
4 Ẹni tí ó ní ọwọ́ mímọ́ àti àyà funfun, ẹni tí kò gbé ọkàn rẹ̀ sókè sí asán tí kò sì búra èké.
The clean of hands, and pure of heart, Who has not lifted up his soul to vanity, Nor has sworn to deceit.
5 Òun ni yóò rí ìbùkún gbà láti ọ̀dọ̀ Olúwa, àti òdodo lọ́wọ́ Ọlọ́run ìgbàlà rẹ̀.
He carries away a blessing from YHWH, Righteousness from the God of his salvation.
6 Èyí ni ìran àwọn tí ń ṣe àfẹ́rí rẹ̀, tí ń ṣe àfẹ́rí rẹ̀, Ọlọ́run Jakọbu. (Sela)
This [is] a generation of those seeking Him. Seeking Your face, O Jacob! (Selah)
7 Ẹ gbé orí yín sókè, háà! Ẹ̀yin ọ̀nà; kí á sì gbe yín sókè, ẹyin ìlẹ̀kùn ayérayé! Kí ọba ògo le è wọlé.
Lift up your heads, O gates! And be lifted up, O perpetual doors! And the King of Glory comes in!
8 Ta ni ọba ògo náà? Olúwa tí ó lágbára tí ó sì le, Olúwa gan an, tí ó lágbára ní ogun.
Who [is] this—“the King of Glory?” YHWH—strong and mighty, YHWH, the mighty in battle.
9 Gbé orí yín sókè, ẹyin ọ̀nà; kí a sì gbé e yín sókè, ẹ̀yin ìlẹ̀kùn ayérayé, kí Ọba ògo le è wọlé wá.
Lift up your heads, O gates! And be lifted up, O perpetual doors! And the King of Glory comes in!
10 Ta ni Ọba ògo náà? Olúwa àwọn ọmọ-ogun Òun ni Ọba ògo náà. (Sela)
Who [is] He—this “King of Glory?” YHWH of hosts—He [is] the King of Glory! (Selah)