< Psalms 22 >

1 Fún adarí orin. Tí ohùn orin “àgbọ̀nrín òwúrọ̀.” Saamu ti Dafidi. Ọlọ́run mi, Ọlọ́run mi, èéṣe tí ìwọ fi kọ̀ mí sílẹ̀? Èéṣe tí o fi jìnnà láti gbà mí là, àní sí igbe ìkérora mi?
En Psalm Davids, till att föresjunga, om hindena som bittida jagad varder. Min Gud, min Gud, hvi hafver du öfvergifvit mig? Jag ryter; men min hjelp är fjerran.
2 Ọlọ́run mi, ní ọ̀sán gangan ni mo kígbe, ṣùgbọ́n ìwọ kò dá mi ní ohùn: àti ní òru èmi kò dákẹ́.
Min Gud, om dagen ropar jag, så svarar du intet; och om nattena tiger jag ock intet.
3 Ṣùgbọ́n síbẹ̀ ẹni mímọ́ ni Ìwọ; ẹni tí ó tẹ ìyìn Israẹli dó.
Men du äst helig, du som bor ibland Israels lof.
4 Àwọn baba ńlá wa ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú rẹ; wọ́n ní ìgbẹ́kẹ̀lé, ìwọ sì gbà wọ́n.
Våre fäder hoppades uppå dig; och då de hoppades, halp du dem ut.
5 Ìwọ ni wọ́n sun ẹkún sí, wọ́n sì ní ìgbàlà; ìwọ ni wọ́n gbẹ́kẹ̀lé, a kò sì dójútì wọ́n.
Till dig ropade de, och vordo hulpne; de hoppades på dig, och vordo icke till skam.
6 Ṣùgbọ́n kòkòrò ní mo jẹ́, kì í sì í ṣe ènìyàn; mo di ẹlẹ́gàn àwọn ènìyàn, ẹlẹ́yà àwọn ènìyàn.
Men jag är en matk, och icke menniska; menniskors gabberi, och folks föraktelse.
7 Gbogbo àwọn tí ó rí mí fi mí ṣe ẹlẹ́yà; wọ́n yọ ètè ẹ̀gàn wọn sí mi, wọ́n sì ń mi orí wọn pé.
Alle de som mig se, bespotta mig, gapa upp med munnen, och rista hufvudet:
8 “Ó gbẹ́kẹ̀ rẹ̀ lé Olúwa; jẹ́ kí Olúwa gbà á là. Jẹ́ kí ó gbà á là, nítorí pé, ó ní ayọ̀ nínú rẹ̀.”
Han klage det Herranom; han hjelpe honom ut, och undsätte honom, om han hafver lust till honom.
9 Síbẹ̀ ìwọ ni ó ti mú mi wá láti inú; ìwọ ni ó mú mi wà láìléwu, nígbà tí mo rọ̀ mọ́ ọmú ìyá mi.
Ty du hafver dragit mig utu mitt moderlif; och vast min tröst, då jag än vid mine moders bröst låg.
10 Ìwọ ni a fi mí lé lọ́wọ́ láti inú ìyá mi wá, nígbà tí ìyá mí sì ti bí mi, ìwọ ni Ọlọ́run mi.
På dig är jag kastad utaf moderlifvet; du äst min Gud, allt ifrå mine moders lif.
11 Má ṣe jìnnà sí mi, nítorí pé ìyọnu súnmọ́ tòsí kò sì ṣí ẹnìkan tí yóò ṣe ìrànlọ́wọ́.
Var icke långt ifrå mig; ty ångest är hardt när; ty här är ingen hjelpare.
12 Ọ̀pọ̀ akọ màlúù yí mi ká; àwọn màlúù alágbára Baṣani rọ̀gbà yí mi ká.
Store stutar hafva belagt mig; fete oxar hafva omhvärft mig.
13 Wọ́n ya ẹnu wọn sì mi bí i kìnnìún tí ń dọdẹ kiri, tí ń ké ramúramù.
De uppgapa med sin mun emot mig, såsom ett glupande och rytande lejon.
14 A dà mí jáde gẹ́gẹ́ bí omi, gbogbo egungun mi ti yẹ̀ kúrò ní oríkèé rẹ̀. Ọkàn mi sì dàbí i ìda; tí ó yọ́ láàrín inú mi.
Jag är utgjuten såsom vatten; all min ben hafva skiljts åt; mitt hjerta i mitt lif är såsom ett smält vax.
15 Agbára mí ti gbẹ bí àpáàdì, ahọ́n mí sì tilẹ̀ mọ́ párí ẹ̀rẹ̀kẹ́ ẹ mi; ìwọ ti tẹ́ mi sínú eruku ikú. (questioned)
Mina krafter äro borttorkade, såsom ett stycke af en potto; och min tunga lådar vid min gom, och du lägger mig uti dödsens stoft.
16 Àwọn ajá yí mi ká; ìjọ àwọn ènìyàn ibi ti ká mi mọ́, wọ́n gún mi lọ́wọ́, wọ́n sì gún mi lẹ́sẹ̀.
Ty hundar hafva kringhvärft mig, och de ondas rote hafver ställt sig omkring mig; mina händer och fötter hafva de genomborrat.
17 Mo lè ka gbogbo àwọn egungun mi; àwọn tìkára wọn ń wò, wọ́n dójú lé mi.
Jag måtte tälja all min ben; men de skåda och se sin lust på mig.
18 Wọ́n pín aṣọ mi láàrín ara wọn àní lórí aṣọ mi ni wọ́n ṣẹ́ gègé.
De byta min kläder emellan sig, och kasta lott om min klädnad.
19 Ṣùgbọ́n ìwọ, Olúwa, má ṣe jìnnà sí mi. Háà! Olùrànlọ́wọ́ ọ̀ mi, yára wá fún àtìlẹ́yìn mi!
Men du, Herre, var icke fjerran; min starkhet, skynda dig till att hjelpa mig.
20 Gba ọkàn mi sílẹ̀ lọ́wọ́ idà, àní ẹ̀mí mi lọ́wọ́ agbára àwọn ajá.
Fria mina själ ifrå svärdet, mina ensamma ifrå hundarna.
21 Gba ọkàn mi sílẹ̀ lọ́wọ́ kìnnìún; kí o sì gbà mí sílẹ̀ lọ́wọ́ ìwo àgbáǹréré.
Hjelp mig utu lejonens mun, och fria mig ifrån enhörningarna.
22 Èmi yóò kéde orúkọ rẹ láàrín arákùnrin àti arábìnrin mi; nínú ìjọ ni èmi yóò máa yìn ọ́.
Jag vill predika ditt Namn minom brödrom; jag vill prisa dig i församlingene.
23 Ẹ̀yin tí ẹ bẹ̀rù Olúwa, ẹ yìn ín! Gbogbo ẹ̀yin ìran Jakọbu, ẹ fi ògo fún un! Ẹ dìde fún un tẹ̀rù tẹ̀rù, ẹ̀yin irú-ọmọ Israẹli!
Lofver Herran, I som frukten honom; honom äre all Jacobs säd, och honom vörde all Israels säd.
24 Nítorí pé òun kò ṣátá, bẹ́ẹ̀ ni kò sì kórìíra ìpọ́njú àwọn tí a ni lára; kò sì fi ojú rẹ̀ pamọ́ fún mi ṣùgbọ́n ó gbọ́ nígbà tí mo ké pè é.
Ty han hafver icke föraktat eller försmått dens fattiga eländhet; och icke förskylt sitt ansigte för honom; och då han ropade till honom, hörde han det.
25 Láti ọ̀dọ̀ rẹ̀ ni ìyìn mi yóò ti wá nínú àjọ ńlá; ẹ̀jẹ́ rẹ̀ ni èmi yóò san níwájú àwọn tí o bẹ̀rù rẹ̀
Dig vill jag prisa, uti den stora församlingene; jag vill betala mitt löfte inför dem som frukta honom.
26 tálákà yóò jẹ yóò sì yó; àwọn tí n wá Olúwa yóò yin jẹ́ kí ẹ̀mí rẹ̀ wà láààyè títí ayérayé!
De elände skola äta, att de mätte varda; och de som efter Herran fråga, skola prisa honom; edart hjerta skall lefva evinnerliga.
27 Gbogbo òpin ayé ni yóò rántí wọn yóò sì yípadà sí Olúwa, àti gbogbo ìdílé orílẹ̀-èdè ni wọn yóò jọ́sìn níwájú rẹ̀,
Tänke derpå alla verldenes ändar, och omvände sig till Herran; och alla Hedningars slägter tillbedje för honom.
28 nítorí ìjọba ni ti Olúwa. Òun ni ó ń pàṣẹ lórí àwọn orílẹ̀-èdè.
Herren hafver ett rike, och han råder ibland Hedningarna.
29 Bẹ́ẹ̀ náà ni gbogbo àwọn olówó ayé wọn yóò ṣe àsè, wọn yóò sì sìn; gbogbo àwọn tí ó wọ inú ilẹ̀ lọ yóò kúnlẹ̀ ní iwájú rẹ̀ àti ẹni tí kò lè pa ọkàn ara rẹ̀ mọ́ ni ààyè.
Alle fete på jordene skola äta, och tillbedja; för honom skola knäböja alle de som i stoft ligga, och de der med bekymmer lefva.
30 Irú-ọmọ rẹ̀ yóò sìn ín; a ó sọ fún àwọn ìran tí ń bọ̀ nípa Olúwa.
Han skall få ena säd, den honom tjenar; om Herran skall man förkunna intill barnabarn.
31 Wọn yóò polongo òdodo rẹ̀ sí àwọn ọmọ tí a kò tí ì bí, wí pé, òun ni ó ṣe èyí.
De skola, komma och predika hans rättfärdighet de folke, som födas skall, att han det gör.

< Psalms 22 >