< Psalms 22 >

1 Fún adarí orin. Tí ohùn orin “àgbọ̀nrín òwúrọ̀.” Saamu ti Dafidi. Ọlọ́run mi, Ọlọ́run mi, èéṣe tí ìwọ fi kọ̀ mí sílẹ̀? Èéṣe tí o fi jìnnà láti gbà mí là, àní sí igbe ìkérora mi?
Au maître-chantre. — Sur «Biche de l'aurore». — Psaume de David. Mon Dieu, mon Dieu, pourquoi m'as-tu abandonné Pourquoi restes-tu loin, sans me secourir, Sans écouter mon gémissement?
2 Ọlọ́run mi, ní ọ̀sán gangan ni mo kígbe, ṣùgbọ́n ìwọ kò dá mi ní ohùn: àti ní òru èmi kò dákẹ́.
Mon Dieu, je crie le jour, — et tu ne réponds pas; La nuit — et je n'ai point de repos.
3 Ṣùgbọ́n síbẹ̀ ẹni mímọ́ ni Ìwọ; ẹni tí ó tẹ ìyìn Israẹli dó.
Cependant, tu es le Saint, Dont le trône est environné des louanges d'Israël.
4 Àwọn baba ńlá wa ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú rẹ; wọ́n ní ìgbẹ́kẹ̀lé, ìwọ sì gbà wọ́n.
C'est en toi que se sont confiés nos pères; Ils ont eu confiance, et tu les as délivrés.
5 Ìwọ ni wọ́n sun ẹkún sí, wọ́n sì ní ìgbàlà; ìwọ ni wọ́n gbẹ́kẹ̀lé, a kò sì dójútì wọ́n.
Ils ont crié vers toi, et ils ont été sauvés. Ils se sont confiés en toi, et ils n'ont pas été déçus.
6 Ṣùgbọ́n kòkòrò ní mo jẹ́, kì í sì í ṣe ènìyàn; mo di ẹlẹ́gàn àwọn ènìyàn, ẹlẹ́yà àwọn ènìyàn.
Mais moi, je suis un ver de terre et non un homme, L'opprobre des hommes et le méprisé du peuple.
7 Gbogbo àwọn tí ó rí mí fi mí ṣe ẹlẹ́yà; wọ́n yọ ètè ẹ̀gàn wọn sí mi, wọ́n sì ń mi orí wọn pé.
Tous ceux qui me voient se moquent de moi; Ils ricanent, ils hochent la tête en disant:
8 “Ó gbẹ́kẹ̀ rẹ̀ lé Olúwa; jẹ́ kí Olúwa gbà á là. Jẹ́ kí ó gbà á là, nítorí pé, ó ní ayọ̀ nínú rẹ̀.”
«Qu'il se repose sur l'Éternel, et l'Éternel le délivrera; Il le sauvera, puisqu'il a mis en lui son affection!»
9 Síbẹ̀ ìwọ ni ó ti mú mi wá láti inú; ìwọ ni ó mú mi wà láìléwu, nígbà tí mo rọ̀ mọ́ ọmú ìyá mi.
Oui, c'est toi qui m'as tiré du sein de ma mère, Et qui m'as fait reposer en paix dans ses bras.
10 Ìwọ ni a fi mí lé lọ́wọ́ láti inú ìyá mi wá, nígbà tí ìyá mí sì ti bí mi, ìwọ ni Ọlọ́run mi.
J'ai été remis entre tes mains dès ma naissance; Dès le sein de ma mère, tu as été mon Dieu.
11 Má ṣe jìnnà sí mi, nítorí pé ìyọnu súnmọ́ tòsí kò sì ṣí ẹnìkan tí yóò ṣe ìrànlọ́wọ́.
Ne t'éloigne pas de moi, quand la détresse est proche, Quand il n'y a personne pour me secourir!
12 Ọ̀pọ̀ akọ màlúù yí mi ká; àwọn màlúù alágbára Baṣani rọ̀gbà yí mi ká.
De nombreux taureaux sont autour de moi; Les robustes taureaux de Basan m'enveloppent.
13 Wọ́n ya ẹnu wọn sì mi bí i kìnnìún tí ń dọdẹ kiri, tí ń ké ramúramù.
Mes ennemis ouvrent leur bouche contre moi, Comme un lion qui déchire et rugit.
14 A dà mí jáde gẹ́gẹ́ bí omi, gbogbo egungun mi ti yẹ̀ kúrò ní oríkèé rẹ̀. Ọkàn mi sì dàbí i ìda; tí ó yọ́ láàrín inú mi.
Je suis comme l'eau qui s'écoule, Et tous mes os se sont disjoints; Mon coeur est comme la cire: Il se fond dans mes entrailles.
15 Agbára mí ti gbẹ bí àpáàdì, ahọ́n mí sì tilẹ̀ mọ́ párí ẹ̀rẹ̀kẹ́ ẹ mi; ìwọ ti tẹ́ mi sínú eruku ikú. (questioned)
Ma vigueur est desséchée comme la brique; Ma langue s'attache à mon palais, Et tu m'as couché dans la poussière de la mort.
16 Àwọn ajá yí mi ká; ìjọ àwọn ènìyàn ibi ti ká mi mọ́, wọ́n gún mi lọ́wọ́, wọ́n sì gún mi lẹ́sẹ̀.
Car des chiens m'ont environné; Une bande de malfaiteurs m'a entouré; Ils ont percé mes mains et mes pieds.
17 Mo lè ka gbogbo àwọn egungun mi; àwọn tìkára wọn ń wò, wọ́n dójú lé mi.
Je pourrais compter tous mes os! Mes ennemis me regardent et m'observent:
18 Wọ́n pín aṣọ mi láàrín ara wọn àní lórí aṣọ mi ni wọ́n ṣẹ́ gègé.
Ils partagent entre eux mes vêtements, Et ils tirent ma robe au sort.
19 Ṣùgbọ́n ìwọ, Olúwa, má ṣe jìnnà sí mi. Háà! Olùrànlọ́wọ́ ọ̀ mi, yára wá fún àtìlẹ́yìn mi!
Toi donc, ô Éternel, ne t'éloigne pas! Toi qui es ma force, accours à mon aide!
20 Gba ọkàn mi sílẹ̀ lọ́wọ́ idà, àní ẹ̀mí mi lọ́wọ́ agbára àwọn ajá.
Délivre mon âme de l'épée, Ma vie, de la dent des chiens!
21 Gba ọkàn mi sílẹ̀ lọ́wọ́ kìnnìún; kí o sì gbà mí sílẹ̀ lọ́wọ́ ìwo àgbáǹréré.
Sauve-moi de la gueule du lion Et des cornes des buffles! Oui, tu m'as exaucé!
22 Èmi yóò kéde orúkọ rẹ láàrín arákùnrin àti arábìnrin mi; nínú ìjọ ni èmi yóò máa yìn ọ́.
J'annoncerai ton nom à mes frères; Je te louerai au milieu de l'assemblée.
23 Ẹ̀yin tí ẹ bẹ̀rù Olúwa, ẹ yìn ín! Gbogbo ẹ̀yin ìran Jakọbu, ẹ fi ògo fún un! Ẹ dìde fún un tẹ̀rù tẹ̀rù, ẹ̀yin irú-ọmọ Israẹli!
Vous qui craignez l'Éternel, louez-le; Vous tous, race de Jacob, glorifiez-le; Craignez-le, vous tous, race d'Israël!
24 Nítorí pé òun kò ṣátá, bẹ́ẹ̀ ni kò sì kórìíra ìpọ́njú àwọn tí a ni lára; kò sì fi ojú rẹ̀ pamọ́ fún mi ṣùgbọ́n ó gbọ́ nígbà tí mo ké pè é.
Car il n'a point méprisé, il n'a pas dédaigné la misère de l'affligé. Il n'a pas détourné de lui son visage; Mais il l'a exaucé quand il criait vers lui.
25 Láti ọ̀dọ̀ rẹ̀ ni ìyìn mi yóò ti wá nínú àjọ ńlá; ẹ̀jẹ́ rẹ̀ ni èmi yóò san níwájú àwọn tí o bẹ̀rù rẹ̀
Tu seras loué par moi dans la grande assemblée; J'accomplirai mes voeux en présence de ceux qui te craignent.
26 tálákà yóò jẹ yóò sì yó; àwọn tí n wá Olúwa yóò yin jẹ́ kí ẹ̀mí rẹ̀ wà láààyè títí ayérayé!
Les malheureux mangeront et seront rassasiés; Ceux qui recherchent l'Éternel le loueront. Que leur coeur revienne à la vie pour toujours!
27 Gbogbo òpin ayé ni yóò rántí wọn yóò sì yípadà sí Olúwa, àti gbogbo ìdílé orílẹ̀-èdè ni wọn yóò jọ́sìn níwájú rẹ̀,
Tous les peuples de la terre se souviendront de l'Éternel, Et ils reviendront à lui; Toutes les familles des nations se prosterneront devant sa face;
28 nítorí ìjọba ni ti Olúwa. Òun ni ó ń pàṣẹ lórí àwọn orílẹ̀-èdè.
Car le règne appartient à l'Éternel, Et il domine sur les nations.
29 Bẹ́ẹ̀ náà ni gbogbo àwọn olówó ayé wọn yóò ṣe àsè, wọn yóò sì sìn; gbogbo àwọn tí ó wọ inú ilẹ̀ lọ yóò kúnlẹ̀ ní iwájú rẹ̀ àti ẹni tí kò lè pa ọkàn ara rẹ̀ mọ́ ni ààyè.
Oui, tous les puissants de la terre se prosterneront devant lui. Tous ceux qui descendent dans la poussière, Ceux qui sont près d'expirer, s'inclineront devant lui.
30 Irú-ọmọ rẹ̀ yóò sìn ín; a ó sọ fún àwọn ìran tí ń bọ̀ nípa Olúwa.
La postérité le servira; On parlera du Seigneur aux générations futures:
31 Wọn yóò polongo òdodo rẹ̀ sí àwọn ọmọ tí a kò tí ì bí, wí pé, òun ni ó ṣe èyí.
Elles viendront et proclameront sa justice. Au peuple qui naîtra, elles annonceront ce qu'il a fait!

< Psalms 22 >