< Psalms 22 >

1 Fún adarí orin. Tí ohùn orin “àgbọ̀nrín òwúrọ̀.” Saamu ti Dafidi. Ọlọ́run mi, Ọlọ́run mi, èéṣe tí ìwọ fi kọ̀ mí sílẹ̀? Èéṣe tí o fi jìnnà láti gbà mí là, àní sí igbe ìkérora mi?
За първия певец по “Кошутата на зората”. Давидов псалом. Боже мой, Боже мой, защо си ме оставил? Защо стоиш далеч и не ми помагаш, Нито внимаваш на думите на охкането ми?
2 Ọlọ́run mi, ní ọ̀sán gangan ni mo kígbe, ṣùgbọ́n ìwọ kò dá mi ní ohùn: àti ní òru èmi kò dákẹ́.
Боже мой, викам денем, но не отговаряш, И нощем, но нямам отдих.
3 Ṣùgbọ́n síbẹ̀ ẹni mímọ́ ni Ìwọ; ẹni tí ó tẹ ìyìn Israẹli dó.
Но Ти си Светият, Който си възцарен между Израилевите хваления.
4 Àwọn baba ńlá wa ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú rẹ; wọ́n ní ìgbẹ́kẹ̀lé, ìwọ sì gbà wọ́n.
На тебе уповаваха бащите ни Уповаваха, и Ти ги избави,
5 Ìwọ ni wọ́n sun ẹkún sí, wọ́n sì ní ìgbàlà; ìwọ ni wọ́n gbẹ́kẹ̀lé, a kò sì dójútì wọ́n.
Към Тебе извикаха, и бяха избавени; На Тебе уповаваха, и не се посрамиха.
6 Ṣùgbọ́n kòkòrò ní mo jẹ́, kì í sì í ṣe ènìyàn; mo di ẹlẹ́gàn àwọn ènìyàn, ẹlẹ́yà àwọn ènìyàn.
А аз съм червей, а не човек, Укоряван от човеците, и презрян от людете.
7 Gbogbo àwọn tí ó rí mí fi mí ṣe ẹlẹ́yà; wọ́n yọ ètè ẹ̀gàn wọn sí mi, wọ́n sì ń mi orí wọn pé.
Всички, които ме гледат, ругаят ме, Отварят устните си, кимват с глава и казват:
8 “Ó gbẹ́kẹ̀ rẹ̀ lé Olúwa; jẹ́ kí Olúwa gbà á là. Jẹ́ kí ó gbà á là, nítorí pé, ó ní ayọ̀ nínú rẹ̀.”
Той упова на Господа: нека го избави; Нека го избави понеже има благоволение в него.
9 Síbẹ̀ ìwọ ni ó ti mú mi wá láti inú; ìwọ ni ó mú mi wà láìléwu, nígbà tí mo rọ̀ mọ́ ọmú ìyá mi.
Но Ти си, Който си ме извадил из утробата; Ти си ме научил да уповавам като бях на майчините си гърди,
10 Ìwọ ni a fi mí lé lọ́wọ́ láti inú ìyá mi wá, nígbà tí ìyá mí sì ti bí mi, ìwọ ni Ọlọ́run mi.
На Тебе бях оставен от рождението си; От утробата на майка ми Ти си мой Бог.
11 Má ṣe jìnnà sí mi, nítorí pé ìyọnu súnmọ́ tòsí kò sì ṣí ẹnìkan tí yóò ṣe ìrànlọ́wọ́.
Да се не отдалечиш от мене; защото скръбта е близо, Понеже няма помощник.
12 Ọ̀pọ̀ akọ màlúù yí mi ká; àwọn màlúù alágbára Baṣani rọ̀gbà yí mi ká.
Много юнци ме обиколиха; Силни васански бикове ме окръжиха.
13 Wọ́n ya ẹnu wọn sì mi bí i kìnnìún tí ń dọdẹ kiri, tí ń ké ramúramù.
Отвориха срещу мене устата си, Като лъв, който граби и реве.
14 A dà mí jáde gẹ́gẹ́ bí omi, gbogbo egungun mi ti yẹ̀ kúrò ní oríkèé rẹ̀. Ọkàn mi sì dàbí i ìda; tí ó yọ́ láàrín inú mi.
Разлях се като вода, И разглобиха се всичките ми кости; Сърцето ми стана като восък, Разтопява се всред вътрешностите ми.
15 Agbára mí ti gbẹ bí àpáàdì, ahọ́n mí sì tilẹ̀ mọ́ párí ẹ̀rẹ̀kẹ́ ẹ mi; ìwọ ti tẹ́ mi sínú eruku ikú. (questioned)
Силата ми изсъхна като черепка, И езикът ми прилепна за челюстите ми; И Ти си ме свел в пръстта на смъртта.
16 Àwọn ajá yí mi ká; ìjọ àwọn ènìyàn ibi ti ká mi mọ́, wọ́n gún mi lọ́wọ́, wọ́n sì gún mi lẹ́sẹ̀.
Защото кучета ме обиколиха; Тълпа от злодейци ме окръжи; Прободоха ръцете ми и нозете ми.
17 Mo lè ka gbogbo àwọn egungun mi; àwọn tìkára wọn ń wò, wọ́n dójú lé mi.
Мога да преброя всичките си кости, Хората се взират в мене и ме гледат.
18 Wọ́n pín aṣọ mi láàrín ara wọn àní lórí aṣọ mi ni wọ́n ṣẹ́ gègé.
Разделиха си дрехите ми, И за облеклото ми хвърлиха жребие.
19 Ṣùgbọ́n ìwọ, Olúwa, má ṣe jìnnà sí mi. Háà! Olùrànlọ́wọ́ ọ̀ mi, yára wá fún àtìlẹ́yìn mi!
Но Ти, Господи, да се не отдалечиш; Ти, сило моя, побързай да ми помогнеш.
20 Gba ọkàn mi sílẹ̀ lọ́wọ́ idà, àní ẹ̀mí mi lọ́wọ́ agbára àwọn ajá.
Избави от меча душата ми, Живота ми от силата на кучето.
21 Gba ọkàn mi sílẹ̀ lọ́wọ́ kìnnìún; kí o sì gbà mí sílẹ̀ lọ́wọ́ ìwo àgbáǹréré.
Избави ме от устата на лъва И от роговете не дивите волове. Ти си ме послушал!
22 Èmi yóò kéde orúkọ rẹ láàrín arákùnrin àti arábìnrin mi; nínú ìjọ ni èmi yóò máa yìn ọ́.
Ще възвестявам името Ти на братята си; Всред събранието ще Те хваля.
23 Ẹ̀yin tí ẹ bẹ̀rù Olúwa, ẹ yìn ín! Gbogbo ẹ̀yin ìran Jakọbu, ẹ fi ògo fún un! Ẹ dìde fún un tẹ̀rù tẹ̀rù, ẹ̀yin irú-ọmọ Israẹli!
Вие, които се боите от Господа, хвалете Го; Цяло Яковово потомство славете Го; И бойте Му се, всички вие от Израилевото потомство.
24 Nítorí pé òun kò ṣátá, bẹ́ẹ̀ ni kò sì kórìíra ìpọ́njú àwọn tí a ni lára; kò sì fi ojú rẹ̀ pamọ́ fún mi ṣùgbọ́n ó gbọ́ nígbà tí mo ké pè é.
Защото не е презрял и не се е отвърнал от скръбта на оскърбения, Нито е скрил лицето Си от него; Но послуша, когато извика той към Него.
25 Láti ọ̀dọ̀ rẹ̀ ni ìyìn mi yóò ti wá nínú àjọ ńlá; ẹ̀jẹ́ rẹ̀ ni èmi yóò san níwájú àwọn tí o bẹ̀rù rẹ̀
От Тебе е гдето принасям хваление в голямото събрание: Ще изпълня обреците си пред ония, които Му се боят.
26 tálákà yóò jẹ yóò sì yó; àwọn tí n wá Olúwa yóò yin jẹ́ kí ẹ̀mí rẹ̀ wà láààyè títí ayérayé!
Смирените ще ядат и ще се наситят; Ще хвалят Господа ония, които Го търсят; Сърцето ви нека живее вечно.
27 Gbogbo òpin ayé ni yóò rántí wọn yóò sì yípadà sí Olúwa, àti gbogbo ìdílé orílẹ̀-èdè ni wọn yóò jọ́sìn níwájú rẹ̀,
Ще си спомнят и ще се обърнат към Господа Всичките земни краища, И ще се покланят пред Тебе Всичките племена на народите;
28 nítorí ìjọba ni ti Olúwa. Òun ni ó ń pàṣẹ lórí àwọn orílẹ̀-èdè.
Защото царството е на Господа, И То владее над народите.
29 Bẹ́ẹ̀ náà ni gbogbo àwọn olówó ayé wọn yóò ṣe àsè, wọn yóò sì sìn; gbogbo àwọn tí ó wọ inú ilẹ̀ lọ yóò kúnlẹ̀ ní iwájú rẹ̀ àti ẹni tí kò lè pa ọkàn ara rẹ̀ mọ́ ni ààyè.
Ще ядат и ще се поклонят всичките богати на земята; Пред Него ще се преклонят всички, които слизат в пръстта; А онзи, който не може да запази живота си,
30 Irú-ọmọ rẹ̀ yóò sìn ín; a ó sọ fún àwọn ìran tí ń bọ̀ nípa Olúwa.
Неговото потомство ще Му слугува; Ще се приказва за Господа на идното поколение.
31 Wọn yóò polongo òdodo rẹ̀ sí àwọn ọmọ tí a kò tí ì bí, wí pé, òun ni ó ṣe èyí.
Ще дойдат и ще известят правдата Му На люде, които ще се родят, казвайки, че Той е сторил това.

< Psalms 22 >